Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ámósì 8:5-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Tí ẹ ń wí pé,“Nígbà wo ni oṣù tuntun yóò paríkí àwa bá à lè ta ọkàkí ọjọ́ ìsinmi kí ó lè dópinkí àwa bá à le ta jéró?”Kí a sì dín ìwọ̀n wa kùkí a gbéraga lórí iye tí a ó tà ákí a sì fi òṣùnwọ̀n èké yàn wọ́n jẹ

6. Kí àwa lè fi fàdákà ra àwọn talákàkí a sì fi bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì ra aláìníkí a sì ta jéró tí a kó mọ́ ilẹ̀

7. Olúwa ti fi ìgbéraga Jákọ́bù búra pé: “Èmi kì yóò gbàgbé ọkan nínú ohun tí wọ́n ṣe.

8. “Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kì yóò ha wárìrì fún èyí?Àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ kì yóò ha sọ̀fọ̀?Gbogbo ilẹ̀ yóò ru sókè bí omi Náílì,yóò sì ru ú sókè pátapáta bí ìkún omia ó sì tì í jáde, a ó sì tẹ̀ ẹ́ rì gẹ́gẹ́ bí odò Éjíbítì.

9. “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa Ọlọ́run wí,“Èmi yóò mú òòrùn wọ̀ ní ọ̀sán,Èmi yóò mú kí ayé ṣókùnkùn ní ọ̀ṣán gangan.

Ka pipe ipin Ámósì 8