Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 59:16-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Òun rí i pé kò sí ẹnìkan,àyà fò ó pé kò sí ẹnìkan láti ṣèrànwọ́;nítorí apá òun tìkálárarẹ̀ ló ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún ara rẹ̀,àti òdodo òun tìkálára rẹ̀ ló gbé e ró.

17. Ó gbé òdodo wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbàya rẹ̀,àti àsíborí ìgbàlà ní oríi rẹ̀;ó gbé ẹ̀wù ẹ̀san wọ̀ó sì yí ara rẹ̀ ní ìtara bí ẹ̀wù.

18. Gẹ́gẹ́ bí ohun tí wọ́n ti ṣe,bẹ́ẹ̀ ni yóò ṣan ánìbínú fún àwọn ọ̀tá rẹ̀àti ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá rẹ̀;òun yóò ṣan án fún àwọn erékùṣù ẹ̀tọ́ wọn.

19. Láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn ènìyàn yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa,àti láti ìlà oòrùn, wọn yóò bọ̀wọ̀ fún ògo rẹ̀.Nítorí òun yóò wá gẹ́gẹ́ bí i rírú omièyí tí èémí Olúwa ń tì lọ.

20. “Olùdáǹdè yóò wá sí Ṣíhónì,sí àwọn tí ó wà ní Jákọ́bù tí óronúpìwàdá ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí.

21. “Àti fún èmi, májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn nìyìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ̀mí mi, tí ó wà nínú yín, àti ọ̀rọ̀ mi tí mo ti fi sí ẹnu yín, kì yóò kúrò lẹ́nu yín, tàbí lẹ́nu àwọn ọmọ yín, tàbí láti ẹnu àwọn ìrandíran wọn láti àkókò yìí lọ àti títí láéláé” ni Olúwa wí.

Ka pipe ipin Àìsáyà 59