Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 49:11-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Èmi yóò sọ gbogbo àwọn oke-ńlá mi di ojú-ọ̀nààti gbogbo òpópónà mi ni a ó gbé ṣókè.

12. Kíyèsí i, wọn yóò wá láti ọ̀nà jínjìnàwọn díẹ̀ láti àríwá àti àwọn díẹ̀láti ìwọ̀ oòrùn,àwọn díẹ̀ láti ẹkùn Áṣíwánì.”

13. Ẹ hó fún ayọ̀, Ẹ̀yin ọ̀run;yọ̀, ìwọ ilẹ̀-ayé;bú sórin, ẹ̀yin òkè-ńlá!Nítorí Olúwa tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínúyóò sì ṣàánú fún àwọn ẹnití a ń pọ́n lójú.

14. Ṣùgbọ́n Ṣíhónì sọ pé, “Olúwa ti kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa ti gbàgbé è mi.”

15. “Ǹjẹ́ abiyamọ ha le gbàgbé ọmọ ọmú rẹ̀kí ó má sì ṣàánú fún ọmọ rẹ̀ tí ó ti bí?Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun le gbàgbéÈmi kì yóò gbàgbé rẹ!

16. Kíyèsí i, mo ti kọ ọ́ sí àtẹ́lẹwọ́ miògiri rẹ wà níwájú mi nígbà gbogbo.

17. Àwọn ọmọ rẹ ti kánjú padà,àti àwọn tí ó sọ ọ́ dahoro ti padà lẹ́yìn rẹ.

18. Gbójú rẹ ṣókè kí o sì wò yíká;gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ kórajọwọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ.Níwọ̀n ìgbà tí mo bá wà láàyè,” ni Olúwa wí,“Ìwọ yóò wọ gbogbo wọ́n gẹ́gẹ́ bí ohun ọ̀ṣọ́;ìwọ yóò wọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí ìyàwó.

19. “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí run ọ́, a sì sọ ọ́ di ahorotí gbogbo ilẹ̀ rẹ sì di ìgbòrò,ní ìsinsìn yìí, ìwọ yóò kéré jù fún àwọn ènìyàn rẹ,bẹ́ẹ̀ ni àwọn ti ó jẹ ó rùn ni yóòwà ni ọ̀nà jínjìn réré.

20. Àwọn ọmọ tí a bí ní àkókò ọ̀fọ̀ rẹyóò sọ ní etígbọ̀ọ́ rẹ,‘Ibi yìí ti kéré jù fún wa;ẹ fún wa láyè sí i tí a ó máa gbé.’

21. Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní ọkàn rẹ pé,‘ta ló bí àwọn yìí fún mi?Mo ti ṣọ̀fọ̀ mo sì yàgàn;A sọ mi di àtìpó a sì kọ̀ mí sílẹ̀.Ta ló wo àwọn yìí dàgbà?A fi èmi nìkan sílẹ̀,ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí níbo ni wọ́n ti wá?’ ”

22. Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí níyìí:“Kíyèsí i, Èmi yóò késí àwọn aláìkọlàÈmi yóò gbé àṣíá mi ṣókè sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn;Wọn yóò kó àwọn ọmọkùnrin yín wá ní apá wọnwọn yóò sì gbé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrinní èjìká wọn.

23. Àwọn ọba ni yóò jẹ́ alágbàtọ́-baba fún ọ,àwọn ayaba wọn ni yóò sì jẹ́ ìyá-alágbàtọ́.Wọn yóò foríbalẹ̀ ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ojú wọn dídàbolẹ̀;wọn yóò máa lá èrùpẹ̀ lẹ́bàá ẹṣẹ̀ rẹ.Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa;gbogbo àwọn tí wọ́n ní ìrètí nínú mini a kì yóò jákulẹ̀.”

24. Ǹjẹ́ a le gba ìkógun lọ́wọ́ jagunjagun,tàbí kí á gba ìgbèkùn lọ́wọ́ akíkanjú?

Ka pipe ipin Àìsáyà 49