Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 29:4-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ní ìrẹ̀sílẹ̀, ìwọ ó sì máa sọ̀rọ̀ láti ilẹ̀ wá;ọ̀rọ̀ rẹ yóò sì máa kùn jáde láti inú erùpẹ̀.Ohun rẹ yóò máa jáde bí i ti iwin láti ilẹ̀ wá,láti inú erùpẹ̀ ni ohùn rẹyóò máa wá wúyẹ́wúyẹ́.

5. Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀tá rẹ, yóò dàbí yanrìn kíkúnná,agbo àwọn aláìláàánú bí ìyàngbò tí a fẹ́ dànù.Lójijì, ní ìṣẹ́jú àáyá,

6. Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò wápẹ̀lú àrá, ilẹ̀ ríri àti ariwo ńláàti ẹ̀fúúfù líle àti iná ajónirunorílẹ̀ èdè tí ó bá Áríẹ́lì jà,tí ó dojú ìjà kọ òun àti ilé olódì rẹ̀tí ó sì dó tì í,yóò dàbí ẹni pé nínú àlá,bí ìran ní òru

7. Lẹ́yìn náà,ọ̀gọ̀rọ̀ ènìyàn tí gbogbo

8. àti bí ìgbà tí ẹni tí ebi ń pa ń lá àlá péòun ń jẹun,ṣùgbọ́n ó jí, ebi rẹ̀ sì wà pẹ̀lúu rẹ̀;àti bí ẹni tí òùngbẹ ń gbẹ lá àlá péòun ń mumi,ṣùgbọ́n nígbà tí ó yajú pẹ́ ẹ́, pẹ̀lú òùngbẹtí kò dáwọ́ dúró ni.Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀ èdètí ń bá òkè Ṣíhónì jà.

9. Ẹ bẹ̀rù kí ẹnu kí ó yà yín,ẹ fọ́ ara yín lójú kí ẹ má sì ríran;ẹ mutí yó kì í ṣe ọtí wáìnì,ẹ ta gbọ̀n-ọ́n gbọ̀n-ọ́n, ṣùgbọ́n kì í se ti ọtí bíà.

10. Olúwa ti mú oorun ìjìká wá sóríi yín:ó ti dì yín lójú (ẹ̀yin wòlíì);ó ti bo oríi yín (ẹ̀yin aríran).

11. Fún un yín gbogbo ìran yìí kò yàtọ̀ sí àwọn ọ̀rọ̀ tí a fi èdìdì dì sínú ìwé kíká. Bí ẹ bá sì fún ẹni tí ó lè ka ìwé kíká náà, tí ẹ sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò lè kà á; a ti dì í ní èdìdì.”

12. Tàbí bí ẹ bá fún ẹni tí kò lè ka ìwé kíká náà tí ẹ sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n kà.”

13. Olúwa wí pé:“Àwọn ènìyàn yìí súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹnu wọnwọ́n sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ètè wọn,ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnnà sí mi.Ìsìn wọn fún mini a gbé ka orí òfin tí àwọnọkùnrin kọ́ ni.

14. Nítorí náà lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò yaàwọn ènìyàn yìí lẹ́nupẹ̀lú ìyanu lórí ìyanu;ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ni yóò ṣègbé,ìmọ̀ àwọn onímọ̀ ni yóò pòórá.”

Ka pipe ipin Àìsáyà 29