Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 1:5-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́?Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe?Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́,gbogbo ọkan yín sì ti pòrúúru.

6. Láti àtẹ́lẹṣẹ̀ yín dé àtàrí yínkò sí àlàáfíà rárá,àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapaàti ojú egbò,tí a kò nùnù tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.

7. Orílẹ̀-èdè yín dahoro,a dáná sun àwọn ìlú yín,oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ runlójú ara yín náà,ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tíàwọn àjèjì borí rẹ̀.

8. Ọmọbìnrin Ṣíónì ni a fi sílẹ̀gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà,gẹ́gẹ́ bí àbá nínú oko ẹ̀gúsí,àti bí ìlú tí a dótì.

9. Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogunbá sẹ́ díẹ̀ kù fún wà,a ò bá ti rí bí Sódómù,a ò bá sì ti dàbí Gòmórà.

10. Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,ẹ̀yin aláṣẹ Sódómù,tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa,ẹ̀yin ènìyàn Gòmórà!

11. “Ọpọ̀lọpọ̀ ẹbọ yínkín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí.“Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísunti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa,Èmi kò ní inú dídùnnínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntànàti ti orúkọ.

12. Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi,ta ni ó bèèrè èyí lọ́wọ́ ọ yín,Gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?

13. Ẹ má mú ọrẹ aṣán wá mọ́!Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi,oṣù tuntun, ọjọ́ ọ̀sẹ̀ àti àwọn àpèjọÈmi kò lè faradà àpèjọ ibi yín wọ̀nyí.

14. Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àpèjẹtí ẹ yà ṣọ́tọ̀ni ọkàn mi kórìíra.Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn,Ó ti sú mi láti máa fara dà wọ́n.

15. Nigbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sóke ni àdúrà,Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín,kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà,Èmi kò ni tẹ́ti sí i.Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.

16. Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́.Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi!Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,

17. kọ́ láti ṣe rere!Wá ìdájọ́ òtítọ́,tù àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú.Ṣàtìlẹ́yìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba,gbà ẹjọ́ opó rò.

Ka pipe ipin Àìsáyà 1