Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 2:34-46 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

34. Bẹ́ẹ̀ ni Bénáyà ọmọ Jéhóíádà sì gòkè lọ, ó sì kọlu Jóábù, ó sì pa á, a sì sin ín ní ilẹ̀ ibojì ara rẹ̀ ní ihà.

35. Ọba sì fi Bénáyà ọmọ Jéhóíádà jẹ olórí ogun ní ipò Jóábù àti Sádókù àlùfáà ní ipò Ábíátarì.

36. Nígbà náà ni ọba ránṣẹ́ sí Ṣíméhì ó sì wí fún un pé, “Kọ́ ilé fún ara rẹ ní Jérúsálẹ́mù, kí o sì máa gbé ibẹ̀, ṣùgbọ́n kí o má sì ṣe lọ sí ibòmíràn.

37. Ọjọ́ tí ìwọ bá jáde, tí o sì kọjá pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kídírónì, kí ìwọ kí ó mọ̀ dájúdájú pé ìwọ yóò kú; ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wà lórí ara rẹ.”

38. Ṣíméhì sì dá ọba lóhùn pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára. Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe bí Olúwa mi ọba ti wí.” Ṣíméhì sì gbé ní Jérúsálẹ́mù fún ìgbà pípẹ́.

39. Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ọdún mẹ́ta, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ Síméì méjì sì sá lọ sọ́dọ̀ Ákíṣì ọmọ Máákà, ọba Gátì, a sì sọ fún Síméì pé, “Àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ méjì wà ní Gátì.”

40. Fún ìdí èyí, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì lọ sọ́dọ̀ Ákíṣì ní Gátì láti wá àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni Síméì sì lọ, ó sì mú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ padà bọ̀ láti Gátì.

41. Nígbà tí a sì sọ fún Sólómónì pé Síméì ti lọ láti Jérúsálẹ́mù sí Gátì, ó sì ti padà,

42. Ọba pe Síméì lẹ́jọ́, ó wí fún un pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ti mú ọ búra ní ti Olúwa, èmi sì ti kìlọ̀ fún ọ pé, ‘Ní ọjọ́ tí ìwọ bá kúrò láti lọ sí ibikíbi, kí o mọ̀ dájú pé ìwọ yóò kú’? Nígbà náà ni ìwọ sì sọ fún mi pé, ‘Ohun tí ìwọ sọ dára. Èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn.’

43. Èéṣe nígbà náà tí ìwọ kò pa ìbúra Olúwa mọ́, àti kí o sì ṣe ìgbọ́ràn sí àṣẹ tí mo pa fún ọ?”

44. Ọba sì tún wí fún Síméì pé, “Ìwọ mọ̀ ní ọkàn rẹ gbogbo búburú tí ìwọ ti ṣe sí Dáfídì baba mi. Báyìí, Olúwa yóò san gbogbo ìṣe búburú rẹ padà fún ọ.

45. Ṣùgbọ́n a ó sì bùkún fún Sólómónì ọba, ìtẹ́ Dáfídì yóò sì wà láìfòyà níwájú Olúwa títí láéláé.”

46. Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Bénáyà ọmọ Jéhóíádà, ó sì jáde lọ, ó sì kọlu Ṣíméhì, ó sì pa á.Ìjọba náà sì wá fi ìdí múlẹ̀ ní ọwọ́ Sólómónì.

Ka pipe ipin 1 Ọba 2