Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Isikiẹli 23:32-44 BIBELI MIMỌ (BM)

32. OLUWA Ọlọrun ní:“ọpọlọpọ ìyà tí mo fi jẹ ẹ̀gbọ́n rẹ ni n óo fi jẹ ọ́,wọn óo fi ọ́ rẹ́rìn-ín,wọn óo sì fi ọ́ ṣẹ̀sín,nítorí ìyà náà óo pọ̀.

33. Ìyà óo jẹ ọ́ lọpọlọpọ,ìbànújẹ́ óo sì dé bá ọ.N óo mú ìpayà ati ìsọdahoro bá ọ,bí mo ṣe mú un bá Samaria, ẹ̀gbọ́n rẹ.

34. O óo jìyà ní àjẹtẹ́rùn,tóbẹ́ẹ̀ tí o óo máa fi àkúfọ́ àwo ìyà tí o bá jẹ ya ara rẹ lọ́mú.Èmi OLUWA Ọlọrun ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

35. Nítorí náà, OLUWA Ọlọrun ní, “Nítorí pé o ti gbàgbé mi, o sì ti kọ̀ mí sílẹ̀, o óo jìyà ìṣekúṣe ati àgbèrè rẹ.”

36. OLUWA bá mi sọ̀rọ̀, ó ní: “Ìwọ ọmọ eniyan ṣé o óo dá ẹjọ́ Ohola ati Oholiba? Nítorí náà fi ìwà ìríra tí wọ́n hù hàn wọ́n.

37. Nítorí wọ́n ti ṣe àgbèrè, wọ́n sì ti paniyan; wọ́n ṣe àgbèrè ẹ̀sìn lọ́dọ̀ àwọn oriṣa wọn, wọ́n sì ti pa àwọn ọmọ wọn ọkunrin tí wọ́n bí fún mi, bọ oriṣa wọn.

38. Èyí nìkan kọ́ ni wọ́n ṣe sí mi, wọ́n sọ ibi mímọ́ mi di eléèérí, wọ́n sì ba àwọn ọjọ́ ìsinmi mi jẹ́.

39. Ní ọjọ́ náà gan-an tí wọ́n pa àwọn ọmọ wọn, tí wọ́n fi wọ́n rúbọ sí oriṣa wọn, ni wọ́n tún wá sí ilé ìsìn mi, tí wọ́n sọ ọ́ di eléèérí. Wò ó! Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ní ilé mi.

40. “Wọ́n tilẹ̀ tún ranṣẹ lọ pe àwọn ọkunrin wá láti òkèèrè, oníṣẹ́ ni wọ́n gbé dìde kí ó lọ pè wọ́n wá; àwọn náà sì wá. Nígbà tí wọ́n dé, ẹ wẹ̀, ẹ kun àtíkè, ẹ tọ́ ojú, ẹ sì ṣe ara yín lọ́ṣọ̀ọ́.

41. Ẹ jókòó lórí àga ọlọ́lá. Ẹ tẹ́ tabili siwaju; ẹ wá gbé turari ati òróró mi lé e lórí.

42. Ogunlọ́gọ̀ àwọn aláìbìkítà ẹ̀dá bẹ̀rẹ̀ sí pariwo lọ́dọ̀ yín, àwọn ọkunrin ọ̀mùtí lásánlàsàn kan sì wá láti inú aṣálẹ̀, wọ́n kó ẹ̀gbà sí àwọn obinrin lọ́wọ́, wọ́n fi adé tí ó lẹ́wà dé wọn lórí.

43. Nígbà náà ni mo wí lọ́kàn ara mi pé, Ǹjẹ́ àwọn ọkunrin wọnyi kò tún ń ṣe àgbèrè, pẹlu àwọn obinrin panṣaga burúkú yìí?

44. Nítorí wọ́n ti tọ̀ wọ́n lọ bí àwọn ọkunrin tí ń tọ aṣẹ́wó lọ. Wọ́n wọlé tọ Ohola ati Oholiba lọ, wọ́n sì bá wọn ṣe àgbèrè.

Ka pipe ipin Isikiẹli 23