Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Títù 2:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ máa kọ́ni ní ẹ̀kọ́ tí ó yè kooro lórí ìgbé ayé onígbàgbọ́ tòótọ́.

2. Kọ́ àwọn àgbà ọkùnrin lẹ́kọ̀ọ́ láti ní ìrònú àti láti jẹ́ ẹni àpọ́nlé àti ẹni ìwọ̀ntúnwọ̀nsì. Wọn gbọdọ̀ jẹ́ ẹni tí ó jinlẹ̀ nínú ìgbàgbọ́, nínú ìfẹ́ àti nínú ìpamọ́ra.

3. Bákan náà, ni kí ó kọ́ àwọn àgbà obìnrin lẹ́kọ̀ọ́ láti kọ́ bí àátí gbé ìgbé-ayé ẹni-ọ̀wọ̀, wọn kò gbọdọ̀ jẹ́ afọ̀rọ̀-kẹ́lẹ́-ba-tẹni-jẹ́ tàbí olùfẹ́ wáìnì mímú, ṣùgbọ́n wọ́n gbọdọ̀ jẹ́ olùkọ́ ohun rere.

4. Nípa èyí, wọ́n yóò lè máa kọ́ àwọn òdóbìnrin láti nífẹ̀ẹ́ àwọn ọkọ wọn àti àwọn ọmọ wọn,

5. láti jẹ́ ẹni ìwọ̀ntúnwọ̀nsì àti ọlọ́kàn mímọ́, kí wọ́n máa ṣe ojúse wọn nínú ilé, wọ́n gbọdọ̀ jẹ́ onínú rere, kí wón sì máa tẹríba fún àwọn ọkọ wọ́n, kí ẹnikẹ́ni máa baà sọ̀rọ̀ òdì sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.

Ka pipe ipin Títù 2