Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Róòmù 15:27-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. Pẹ̀lú ayọ̀ ni wọ́n ń se èyí, nítorí wọ́n gbà wí pé, wọ́n jẹ́ ajigbésè fún wọn. Nítorí bí ó bá se pé a fi àwọn aláìkọlà se alájọni nínú ohun ẹ̀mí wọn, ajigbèsè sì ni wọn láti fi ohun ti ara ta wọ́n lọ́rẹ.

28. Nítorí náà, nígbà tí mo bá ti se èyí tán tí mo bá sì di ẹ̀dìdì èso náà fún wọn tán, èmi yóò gba ti ọ̀dọ̀ yín bí mo bá ń lọ sí orílẹ̀ èdè Sípáníà.

29. Mo sì mọ̀ pé nígbà tí mo bá dé ọ̀dọ̀ yín, èmi yóò wà ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìbùkùn Kírísítì.

30. Èmí rọ̀ yín, ẹ̀yin ará, nítorí Olúwa wa Jésù Kírísítì, àti nítorí ìfẹ́ Ẹ̀mí, kí ẹ̀yin kí ó kún mi láti bá mi làkàkà nínú àdúrà yín sí Ọlọ́run fùn mi.

31. Kí a lè kó mi yọ kúrò lọ́wọ́ àwọn aláìgbàgbọ́ ní Jùdíà àti kí isẹ́ ìránsẹ́ tí mo ní sí Jérúsálẹ́mù le jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn mímọ́ níbẹ̀.

32. Nítorí náà, nípa ìfẹ́ Ọlọ́run kí èmi le fi ayọ̀ tọ̀ yín wa, kí pọ̀ pẹ̀lú yín ní ìtura.

33. Kí Ọlọ́run àlàáfíà wà pẹ̀lú gbogbo yín. Àmín.

Ka pipe ipin Róòmù 15