Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Róòmù 15:23-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

23. Ṣùgbọ́n báyìí tí kò tún sí ibòmíràn fún mi mọ́ ní agbègbè yìí, tí èmi sì ti ń pòùngbẹ láti ọdún púpọ̀ sẹ́yìn láti tọ̀ yín wá,

24. mo gbèrò láti se bẹ́ẹ̀ nígbà tí mo bá lọ sí orílẹ̀ èdè Sípáníà. Èmi yóò bẹ̀ yín wò ní ọ̀nà ìrìnàjò mi, lẹ́yìn tí a bá sì gbádùn ara wa fún ìgbà díẹ̀, ẹ ó kún mi ọ́wọ́ nínú ìrìnàjò mi láti dé ibẹ̀.

25. Ṣùgbọ́n ní báyìí, mo ń lọ nínú ìrìnàjò sí ìlú Jérúsálẹ́mù láti sé ìránsẹ́ fún àwọn ènìyàn mímọ́ níbẹ̀.

26. Nítorí pé àwọn tí ó wà ní agbégbé Makedóníà àti agbégbé Ákáyà ti kó ẹ̀bùn jọ fún àwọn talákà tí ó wà ní àárín àwọn ènìyàn mímọ́ ní Jérúsálẹ́mù.

27. Pẹ̀lú ayọ̀ ni wọ́n ń se èyí, nítorí wọ́n gbà wí pé, wọ́n jẹ́ ajigbésè fún wọn. Nítorí bí ó bá se pé a fi àwọn aláìkọlà se alájọni nínú ohun ẹ̀mí wọn, ajigbèsè sì ni wọn láti fi ohun ti ara ta wọ́n lọ́rẹ.

28. Nítorí náà, nígbà tí mo bá ti se èyí tán tí mo bá sì di ẹ̀dìdì èso náà fún wọn tán, èmi yóò gba ti ọ̀dọ̀ yín bí mo bá ń lọ sí orílẹ̀ èdè Sípáníà.

29. Mo sì mọ̀ pé nígbà tí mo bá dé ọ̀dọ̀ yín, èmi yóò wà ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìbùkùn Kírísítì.

30. Èmí rọ̀ yín, ẹ̀yin ará, nítorí Olúwa wa Jésù Kírísítì, àti nítorí ìfẹ́ Ẹ̀mí, kí ẹ̀yin kí ó kún mi láti bá mi làkàkà nínú àdúrà yín sí Ọlọ́run fùn mi.

Ka pipe ipin Róòmù 15