Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mátíù 21:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Bí wọ́n ti sún mọ́ Jérúsalẹmu, tí wọ́n dé ìtòòsí ìlú Bẹ́tífágè ní orí òkè Ólífì, Jésù sì rán àwọn ọmọ-ẹ̀yìn méjì,

2. Ó wí fún wọn pé, “Ẹ lọ sí ìletò tó wà ni tòòsí yín, ẹ̀yin yóò rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ti wọ́n so pẹ̀lú ọmọ rẹ̀ lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Ẹ tú wọn, kí ẹ sì mú wọn wá fún mi.

3. Bí ẹnikẹ́ni bá sì béèrè ìdí tí ẹ fi ń ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ sáà wí pé, Olúwa ní wọn-ọ́n lò, òun yóò sì rán wọn lọ.”

4. Èyí ṣẹlẹ̀ láti mú àsọtẹ́lẹ̀ wòlíì ṣẹ pé:

5. “Ẹ sọ fún ọmọbìnrin Síónì pé,‘Wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,ní ìrẹ̀lẹ̀, ó ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,àti lórí ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.’ ”

6. Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn náà sí lọ, wọ́n ṣe bí Jésù ti sọ fún wọn

7. Wọ́n sì mú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà pẹ̀lú ọmọ rẹ̀, wọ́n tẹ́ aṣọ lé e, Jésù si jókòó lórí rẹ̀.

8. Ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn sì tẹ́ aṣọ wọn sí ojú ọ̀nà níwájú rẹ̀, ẹlòmíràn sẹ́ ẹ̀ka igi wẹ́wẹ́ wọ́n sì tẹ́ wọn sí ojú ọ̀nà.

9. Ọ̀pọ̀ ènìyàn ń lọ níwájú rẹ̀ àti lẹ́yìn rẹ̀ pẹ̀lú ń kígbe pé,“Hòsánà fún ọmọ Dáfídì!”“Olùbùkún ni fún ẹni tí ó ń bọ̀ ní orúkọ Olúwa!”“Hòsánà ní ibi gíga jùlọ!”

Ka pipe ipin Mátíù 21