Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Máàkù 9:40-50 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

40. Nítorí ẹni tí kò bá kọ ojú ìjà sí wa, ó wà ní ìhà tiwa

41. Lóòótọ́ ni mo sọ fún ún yín bí ẹnikẹ́ni bá fún un yín ní ife omi kan nítorí pé ẹ jẹ́ ti Kírísítì, dájúdájú ẹni náà kì yóò sọ èrè rẹ̀ nù bí ó ti wù kí ó rí.

42. “Ṣùgbọ́n ti ẹnikẹ́ni bá mú ọ̀kan nínú àwọn ọmọ kékeré wọ̀nyí tí ó gbà mí gbọ́ sìnà nínú ìgbàgbọ́ rẹ́, ó sàn fún un kí a so òkúta ńlá mọ́ ọn ni ọ̀run, kí a sì sọ ọ́ sínú òkun.

43. Bí ọwọ́ rẹ bá mú ọ kọsẹ̀, gé e sọnù, ó sàn fún ọ kí o gbé títí ayé àìnípẹ̀kun pẹ̀lú ọwọ́ kan ju kí a gbé ọ sínú iná àjóòkú ọ̀run àpáàdì pẹ̀lú ọwọ́ méjèèjì.

44. Níbi tí kòkòrò wọn kì í kú tí iná nàá kì í kú

45. Bí ẹsẹ̀ rẹ bá sì mú ọ kọsẹ̀, gé é sọnú, ó sàn kí ó di agẹ́sẹ̀, kí o sì gbé títí ayé àìnípẹ̀kun ju kí o ní ẹṣẹ̀ méjì tí ó gbé ọ lọ sí ọ̀run àpáàdì.

46. Níbi tí kòkòrò wọn kì í kú, tí iná nàá kì í sì í ku

47. Àti pé, bí ojú rẹ bá mú ọ kọsẹ̀, yọ ọ́ sọnù, ó sàn kí o wọ ìjọba Ọlọ́run pẹ̀lú ojú kan ju kí ó ní ojú méjì kí ó sì lọ sí inú iná ọ̀run àpáàdì.

48. Níbi ti“ ‘kòkòrò wọn kìí kú,,tí iná kì í sì í kú.’

49. Níbẹ̀ ni a ó ti fi iná dán ẹnìkọ̀ọ̀kan wò

50. “Iyọ̀ dára, ṣùgbọ́n tí ó bá sọ agbára adùn rẹ̀ nù, báwo ni ẹ ṣè lè padà mu un dùn? Ẹ ni iyọ̀ nínú ara yín, ki ẹ sì máa gbé ni àlàáfíà pẹ̀lú ara yín.”

Ka pipe ipin Máàkù 9