9. Òun sì ń bọ̀ pẹ̀lú Ónísímù, arákùnrin olóòótọ́ àti olùfẹ́, ẹni tí í ṣe ọ̀kan nínú yín. Àwọn ní yóò sọ ohun gbogbo tí à ń ṣe níhìn-ín-yìí fún un yín.
10. Árísítákù, ẹlẹgbẹ́ mí nínú túbú kí i yín, àti Máàkù, ọmọ arábìnrin Bánábà (Nípaṣẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ti gba àṣẹ; bí ó bá sì wá sí ọ̀dọ̀ yín, ẹ gbà á).
11. Àti Jésù, ẹni tí à ń pè ní Jọsítọ́sì, ẹni tí ń ṣe ti àwọn onílà. Àwọn wọ̀nyí nìkan ni olùbá ṣiṣẹ́ mí fún ìjọba Ọlọ́run, àwọn ẹni tí ó tí já sí ìtùnú fún mi.
12. Épáfúrà, ẹni tí ń ṣe ọ̀kan nínú yín àtiìránṣẹ́ Kírísítì kí í yín. Òun fí ìwàyájà gbàdúrà nígbà gbogbo fún-ún yín, kí ẹ̀yin kí ó lè dúró ní pípé nínú ohun gbogbo nínú ìfẹ́ Ọlọ́run.
13. Nítorí mo jẹ́rìí rẹ̀ pé ó ń ṣisẹ́ kárakára fún yín, àti fún àwọn tí ó wà ní Laodékíà, àti àwọn tí ó wà ní Hírápólì.
14. Lúùkù, aràkùnrin wa ọ̀wọ́n, oníṣègùn, àti Dẹ́mà ki í yín.
15. Ẹ kí àwọn ará tí ó wà ńi Laodékíà, àti Nímífásì, àti ìjọ tí ó wà ní ilé rẹ̀.
16. Nígbà tí a bá sì ka ìwé yìí ní àárin yín tan, kí ẹ mú kí a kà á pẹ̀lú nínú ìjọ Laodékíà; ẹ̀yin pẹ̀lú sì ka èyí tí ó ti Laodékíà wá.
17. Kí ẹ sì wí fún Áríkípù pé, “Kíyèsi iṣẹ́ ìránṣẹ́ tí ìwọ ti gbà nínú Olúwa kí o sì ṣe é ní kíkún.”
18. Ìkíni láti ọwọ́ èmi Pọ́ọ̀lù. Ẹ máa ránti ìdè mi. Kí oore-ọ̀fẹ́ kí ó wà pẹ̀lú yín. Àmín. A kọ ọ́ láti Rómù lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ará Kólósè láti ọwọ́ Tíkíkù àti Ónísímù.