Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ìfihàn 11:10-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Àti àwọn tí o ń gbé orí ilẹ̀ ayé yóò sì yọ̀ lé wọn lórí, wọn yóò sì ṣe àríyá, wọn ó sì ta ara wọn lọ́rẹ; nítorí tí àwọn wòlíì méjèèjì yìí dá àwọn tí o ń bẹ lórí ilẹ̀ ayé lóró,

11. Àti lẹ́yìn ijọ́ mẹ́ta àti ààbọ̀ náà, ẹ̀mí iyè láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá wọ inú wọn, wọn sì dìde dúró ni ẹṣẹ̀ wọn; ẹ̀rù ńlá sì ba àwọn tí o rí wọn.

12. Wọn sì gbọ́ ohùn ńlá kan láti ọ̀run wá ń wí fún wọn pé, “Ẹ gòkè wá ìhín!” Wọn sì gòkè lọ sí ọ̀run nínú ìkúukúù àwọsánmà; lójú àwọn ọ̀ta wọn.

13. Ní wákàtí náà ìmìmì-ilẹ̀ ńlá kan sì mì, ìdámẹ̀wàá ìlú náà sì wó, àti nínú ìmìmì-ilẹ̀ náà ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn ní a pa; ẹ̀rù sì ba àwọn ìyókù, wọn sì fi ògo fún Ọlọ́run ọ̀run.

14. Ègbé kéjì kọjá; sì kìyèsí i, ègbé kẹta sì ń bọ̀ wá kánkán.

15. Ańgẹ́lì kéje sì fọn ìpè; a sì gbọ́ ohùn ńlá láti ọ̀run, wí pé,“Ìjọba ayé di ti Olúwa wá, àti tí Kírísítì rẹ̀;òun yóò sì jọba láé àti láéláé!”

16. Àwọn àgbà mẹ́rìnlélógún náà tí wọn jókòó níwájú Ọlọ́run lórí ìtẹ́ wọn, dojúbolẹ̀, wọn sì sin Ọlọ́run,

Ka pipe ipin Ìfihàn 11