Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kọ́ríńtì 13:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èyí ni ó dí ìgbà kẹta tí èmi ń tọ̀ yín wá. Ní ẹnu ẹlẹ́rìí méjì tàbí mẹ́ta ni a ó fí ìdí ọ̀rọ̀ gbogbo múlẹ̀.

2. Mo ti sọ fún yín ṣáájú, mo sì ń sọ fún yín tẹ́lẹ̀, bí ẹni pé mo wà pẹ̀lú yín nígbà kejì, àti bí èmi kò ti sí lọ́dọ̀ yín ní ìsinsin yìí, mo kọ̀wé sí àwọn tí ó ti ṣẹ̀ náà, àti sí gbogbo àwọn ẹlòmíran, pé bí mo bá tún padà wá, èmi kì yóò dá wọn sí.

3. Níwọ̀n bí ẹ̀yin tí ń wá àmì Kírísítì ti ń sọ̀rọ̀ nínú mi, ẹni tí kì í ṣe àìlera sí yin, ṣùgbọ́n tí ó jẹ́ agbára nínú yín.

4. Nítorí pé a kàn án mọ́ àgbélébùú nípa àìlera, ṣùgbọ́n òun wà láàyè nípa agbára Ọlọ́run. Nítorí àwa pẹ̀lú já sí aláìlera nínú rẹ̀, ṣùgbọ́n àwa yóò wà láàyè pẹ̀lú rẹ̀ nípa agbára Ọlọ́run sí yín.

5. Ẹ máa wádìí ara yín, bí ẹ̀yin bá wà nínú ìgbàgbọ́; ẹ máa dán ara yín wò. Tàbí ẹ̀yin fúnra yín kò mọ ara yín pé Jésù Kírísítì wá nínú yín? Àfi bí ẹ̀yin bá jẹ́ àwọn tí a tanù.

6. Ṣùgbọ́n mo ní ìgbẹ́kẹ̀lé pé ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, àwa kì í ṣe àwọn tí a tanù.

Ka pipe ipin 2 Kọ́ríńtì 13