Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Pétérù 5:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Àwọn alàgbà tí ń bẹ láàrin yín ni mo gbànímọ̀ràn, èmi ẹni tí ń ṣe alàgbà bí ẹ̀yin, àti ẹlẹ́rìí ìyà Kírísítì, àti alábàápín nínú ògo tí a ó fihàn:

2. Ẹ máa tọ́jú agbo Ọlọ́run tí ń bẹ láàrin yín, ẹ máa bojútó o, kì í ṣe àfipáse, bí kò se tìfẹ́tìfẹ́; kó má sì jẹ́ fún èrè ijẹkújẹ, bí kò ṣe pẹ̀lú ìyè inú tí ó múra tan.

3. Bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe bí ẹni tí ń lo agbára lórí ìjọ, ṣùgbọ́n kí ẹ ṣe ara yín ní àpẹẹrẹ fún agbo.

4. Nígbà tí olórí Olùsọ́-àgùntàn bá sì fi ara hàn, ẹ̀yin ó gba adé ògo ti kì í ṣá.

5. Bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú, ẹ̀yin ọ̀dọ́, ẹ tẹriba fún àwọn alàgbà. Àní, gbogbo yín ẹ máa tẹriba fún ara yín kí ẹ fi ìrẹ̀lẹ̀ wọ ara yin ní aṣọ: nítorí“Ọlọ́run kọ ojú ìjà sí àwọn agbéraga,ṣùgbọ́n ó ń fi oore-ọ̀fẹ́ fún àwọn onírẹ̀lẹ̀.”

6. Nítorí náà, ẹ rẹ ara yin sílẹ̀ lábẹ́ ọwọ́ agbára Ọlọ́run, kí òun lè gbe yín ga lákòókò.

7. Ẹ máa kó gbogbo àníyàn yín lé e; nítorí tí òun ń ṣe ìtọ́jú yín.

8. Ẹ máa wà ni àìrékọjá, ẹ máa ṣọ́ra; nítorí Èṣù ọ̀ta yín, bí kínnìún tí ń ke ramúramù, o ń rìn káàkiri, ó ń wa ẹni tí yóò pajẹ.

9. Ẹ kọ ojú ìjà sí i pẹ̀lú ìdúró ṣinṣin nínú ìgbàgbọ́, bí ẹ̀yin ti mọ̀ pé ìyà kan-náà ni àwọn ará yín tí ń bẹ nínú ayé ń jẹ.

Ka pipe ipin 1 Pétérù 5