Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 2:1-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígba tí ẹ̀mí tọ̀ yín wá, ẹ̀yin ará, kì í ṣe nípa ọ̀rọ̀ gíga àti ọgbọ́n gíga ni mo fi bá yín sọ̀rọ̀, nígbà tí èmi ń sọ̀rọ̀ ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run fún un yín.

2. Nítorí tí èmi kì yóò mọ ohunkóhun nígbà ti mo wà láàrin yín bí kò ṣe Jésù Kírísítì, ẹni tí a kàn mọ́ àgbélébùú.

3. Èmi sì tọ̀ yín wá ni àìlera, àti ní ẹ̀rù, àti ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwárìrì.

4. Ìwáàsu mi àti ẹ̀kọ́ mi, kì í ṣe nípa ọgbọ́n ènìyàn àti ọ̀rọ̀ tí a fi ń yí ènìyàn lọ́kàn padà, bí kò ṣe nípa ìfihàn agbára Ẹ̀mí.

5. Kí ìgbàgbọ́ yín kí ó má ṣe dúró lórí ọgbọ́n ènìyàn, ṣùgbọ́n kí ó dúró lórí agbára Ọlọ́run.

6. Ṣùgbọ́n àwa ń sọ̀rọ̀ ọgbọ́n láàrin àwọn tí a pè; ṣùgbọ́n kì í ṣe ọgbọ́n ti ayé yìí tàbí ti àwọn olórí ayé yìí, èyí tí yóò di asán

7. Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa ń sọ̀rọ̀ ọgbọ́n ti Ọlọ́run tó farasin, ọgbọ́n tí ó ti farapamọ́, èyí tí Ọlọ́run ti lànà sílẹ̀ ṣáájú ìpìlẹ̀ṣẹ̀ ayé fún ògo wa.

8. Èyí ti ẹnikẹ́ni nínú àwọn aláṣẹ ayé yìí kò mọ̀: ìbá ṣe pé wọ́n mọ̀, wọn kì bá tún kan ọba ògo mọ́ àgbélébùú.

9. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé:“Ojú kò tíì rí,etí kò tí í gbọ́,kò sì ọkàn tí ó tí í mọ̀ènìyànohun tí Ọlọ́run tí pèsè sílẹ̀ fún àwọn tí o fẹ́ Ẹ.”

10. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti fi í hàn fún wa nípasẹ̀ Ẹ̀mi rẹ̀.Ẹ̀mí á máa wádìí ohun gbogbo, kódà àwọn àsírí Ọlọ́run tó jinlẹ̀ jùlọ.

11. Ta ni nínú ènìyàn tí ó mọ èrò ọkàn ènìyàn kan, bí kò ṣe ẹ̀mí ènìyàn tí ó wà nínú rẹ̀? Bákan náà, kò sí ẹni tó mọ àwọn èrò Ọlọ́run, bíkòse Ẹ̀mí Ọlọ́run fúnraa rẹ̀.

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 2