Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 7:18-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Nígbà tí èmi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi bá fun fèrè wa, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin náà ni gbogbo igun ibùdó tí ẹ̀ bá wà kí ẹ fun àwọn fèrè yín kí ẹ sì hó pé, ‘Fún Ọlọ́run àti fún Gídíónì.’ ”

19. Gídíónì àti àwọn ọgọ́rùn-ún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ dé òpin ibùdó àwọn ará Mídíánì ní nǹkan bí agogo méjìlá padà. Wọ́n fun fèrè wọn, wọ́n sì tún fọ́ àwọn ìkòkò tí ó wà ní ọwọ́ mọ́lẹ̀.

20. Àwọn ẹgbẹ́ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta fun fèrè wọn, wọ́n tún fọ́ àwọn ìkòkò wọn mọ́lẹ̀. Wọ́n mú àwọn àtùpà iná wọn ní ọwọ́ òsì wọn àti fèrè tí wọ́n ń fun ní ọwọ́ ọ̀tún wọn. Wọ́n pariwo hè è pé, “Idà kan fún Olúwa àti fún Gídíónì!”

21. Nígbà tí ọkùnrin kọ̀ọ̀kan dúró ní ipò rẹ̀ yí ibùdó àwọn Mídíánì ká, gbogbo àwọn ọmọ ogun Mídíánì ń sá káàkiri, wọ́n ń pariwo bí wọ́n ṣe ń sálọ.

22. Nígbà tí àwọn ọ̀ọ́dúnrún (300) ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì fun fèrè wọn, Olúwa da ojú ọkùnrin kọ̀ọ̀kan kọ ẹnìkejì rẹ̀ àti sí gbogbo ojú ọwọ́ wọn. Àwọn ọmọ ogun sì sá títí dé Bẹti Sítà ní ọ̀nà Ṣérérà títí lọ dé ìpínlẹ̀ Abeli-Méhólà ní ẹ̀bá Tábátì.

23. Gbogbo àwọn ọmọ ogun Ísírẹ́lì láti ẹ̀yà Náfítalì, Ásérì àti gbogbo Mànásè ni Gídíónì ránṣẹ́ sí, wọ́n wá wọ́n sì lé àwọn ará Mídíánì.

24. Gídíónì tún ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè Éfúráímù wí pé, “Ẹ jáde wá bá àwọn ará Mídíánì jà, kí ẹ tètè gba àwọn omi Jọ́dánì títí dé Bẹti Bárà kí wọ́n tó dé bẹ̀.”Báyìí ni a ṣe pe gbogbo ọkùnrin ológun Éfúráímù jáde tí wọ́n sì gba gbogbo àwọn àbáwọdò Jọ́dánì títí dé Bẹti Bárà.

25. Wọ́n mú méjì nínú àwọn olórí àwọn ará Mídíánì, àwọn náà ni Órébù àti Ṣéébù. Wọ́n pa Órébù nínú àpáta Órébù, wọ́n sì pa Ṣéébù níbi tí àwọn ènìyàn ti mọ̀ fún wáìnì tí a ń pè ní ìfúntí Ṣéébù. Wọ́n lé àwọn ará Mídíánì, nígbà tí wọ́n gbé orí Órébù àti Ṣéébù tọ Gídíónì wá ẹni tí ó wà ní ìhà kejì Jọ́dánì.

Ka pipe ipin Onídájọ́ 7