Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 7:1-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Jérúb-báálì (èyí ni Gídíónì) pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kó ogun jọ lẹ́bá a oríṣun Háṣódì. Àwọn ogun Mídíánì sì wà ní apá àríwá tí wọ́n ní àfonífojì tí ó wà ní ẹ̀bá òkè Mórè.

2. Olúwa wí fún Gídíónì pé, “Àwọn ọmọ ogun tí o kó jọ sọ́dọ̀ ti pọ̀ jù fún mi láti fi àwọn ogun Mídíánì lé wọn lọ́wọ́, kí Ísírẹ́lì má ba à gbé ara rẹ̀ ga sí mi wí pé agbára òun ni ó gbà á là,

3. sì kéde sí àwọn ènìyàn nísinsìn yìí pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbọ̀n, tí ó sì ń bẹ̀rù lè padà sẹ́yìn, kí ó sì kúrò lórí òkè Gílíádì.’ ” Báyìí ni Gídíónì ṣe ya àwọn ènìyàn náà. Ẹgbẹ̀rúnméjìlélógún ọkùnrin sì padà sẹ́yìn àwọn ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì dúró.

4. Olúwa sì tún sọ fún Gídíónì pé, “Àwọn ènìyàn yìí sì tún pọ̀ jù. Kó wọn lọ sí ibi tí omi wà, èmi yóò sì yọ̀rọ̀ wọn níbẹ̀ fún ọ. Bí mo bá wí pé eléyìí yóò bá ọ lọ yóò lọ, ṣùgbọ́n tí mo bá sọ pé, ‘Eléyìí kò ní bá ọ lọ,’ òun kò gbọdọ̀ lọ.”

5. Gídíónì sì kó àwọn ọkùnrin náà lọ sí ibi ìṣun omi. Níbẹ̀ ni Olúwa ti wí fún un pé, “Kí ó pín àwọn ènìyàn náà sí ọ̀nà méjì. Ya àwọn tí ó fi ahọ́n wọn lá omi bí ajá kúrò lára àwọn tí ó kúnlẹ̀ láti mu omi pẹ̀lú ọwọ́ wọn.”

6. Ọ̀ọ́dúnrún (300) ọkùnrin ni ó lá omi pẹ̀lú ahọn wọn. Gbogbo àwọn ìyókù ni ó kúnlẹ̀ láti mu mi.

7. Olúwa wí fún Gídíónì pé, “Àwọn ọ̀ọ́dúnrún (300) ọkùnrin tí ó lá omi ni èmi yóò lò láti gbà yín là àti láti fi ogun Mídíánì lé yín lọ́wọ́. Jẹ́ kí àwọn tókù padà sí ilé wọn.”

8. Báyìí ni Gídíónì ṣe dá àwọn Ísírẹ́lì tí ó kù padà sí àgọ́ wọn, ṣùgbọ́n ó dá àwọn ọ̀ọ́dúrún ọkùnrin náà dúró. Àwọn wọ̀nyí sì gba gbogbo ohun èlò àti fèrè àwọn tí ó ti padà.Ibùdó ogun àwọn Mídíánì wà ní àfonífojì ní ìṣàlẹ̀. Ibi tí ó wà.

9. Ní òru ọjọ́ náà Olúwa sọ fún Gídíónì pé, “Dìde, dojú ogun kọ ibùdó ogun àwọn ará Mídíánì nítorí èmi yóò fi lé ọ lọ́wọ́.

10. Ṣùgbọ́n bí ẹ̀rù àti kọlù wọ́n bá ń bà ọ́, yọ́ wọ ibùdó wọn lọ kí o mú Púrà ìránṣẹ́ rẹ lọ́wọ́

Ka pipe ipin Onídájọ́ 7