Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ọbadáyà 1:10-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Nítorí ìwà ipá sí Jákọ́bù arákùnrin rẹ,ìtìjú yóò bò ọ,a ó sì pa ọ run títí láé.

11. Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apákan,ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ,tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹtí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jérúsálẹ́mù,ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.

12. Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ,ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Júdà,ní ọjọ́ ìparun wọnìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀ní ọjọ́ wàhálà wọn.

13. Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ,ní ọjọ́ àjálù wọn.Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀nínu ìdàmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn.Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó,ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.

14. Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nàláti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò.Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó sẹ́kùwọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.

15. “Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílélórí gbogbo àwọn aláìkọlà.Bí ìwọ ti se, bẹ́ẹ̀ ni a ó se sí ìwọ náà;ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.

16. Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ se mu lórí òkè mímọ́ miBẹ́ẹ̀ ni gbogbo aláìkọlà yóò máa mu títíWọn yóò mu wọn yóò sì gbémìWọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò wà rí

17. Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè SíónìWọn yóò sì jẹ́ mímọ́àti ilé Jákọ́bù yóò sì ní ìní wọn

Ka pipe ipin Ọbadáyà 1