Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 27:4-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Kín ni ó dé tí orúkọ baba wa yóò parẹ́ nínú ìdílé rẹ̀ nítórí pé kò ní ọmọkùnrin? Fún wa ní ilẹ̀ ìní láàrin àwọn arakùnrin baba wa.”

5. Nígbà náà Mósè mú ọ̀rọ̀ wọn wá ṣíwájú Olúwa.

6. Olúwa sì wí fún un pé,

7. “Ohun tí àwọn ọmọbìnrin Ṣélófénátì ń sọ tọ̀nà. Ó gbọdọ̀ fún wọn ní ogún ìní ti baba wọn.

8. “Sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ‘Tí ọkùnrin kan bá kú tí kò sì fi ọmọkùnrin sáyé, ẹ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀.

9. Tí kò bá ní ọmọbìnrin, fi ohun ìní rẹ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀.

10. Tí kò bá ní arakùnrin, fi ogún ìní rẹ̀ fún arákùnrin baba rẹ̀.

11. Tí baba rẹ̀ kò bá ní arákùnrin, fún ará ilé rẹ̀ tí ó bá súnmọ́ jù ní ìdílé rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀, kí ó lè jogún rẹ̀. Èyí gbọdọ̀ jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti paláṣẹ fún Mósè.’ ”

12. Nígbá náà Olúwa sọ fún Mósè pé, “Lọ sì orí òkè Ábárímù yìí, kí o sì lọ wo ilẹ̀ tí mo fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.

13. Lẹ́yìn ìgbà tí o bá sì ti rí i, ìwọ náà yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ gẹ́gẹ́ bí Árónì arákùnrin rẹ ṣe ṣe,

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 27