Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nehemáyà 13:20-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Ṣíbẹ̀, àwọn tí ń tà àti àwọn tí ń rà sùn ẹ̀yìn odi Jérúsálẹ́mù ní ẹ̀ẹ̀kan tàbí ẹ̀ẹ̀méjì.

21. Ṣùgbọ́n mo kìlọ̀ fún wọn pé, “È é tí jẹ́ ti ẹ̀yin fi ń sùn ní ẹ̀yin odi ní òru? Bí ẹ̀yìn bá tún dán an wò mọ́, èmi yóò fi ọwọ́ líle mú un yín.” Láti ọjọ́ náà lọ, wọn kò sì wá ní ọjọ́ ìsinmi mọ́.

22. Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún àwọn ọmọ Léfì pé kí wọn ya ara wọn sí mímọ́, kí wọn sì ṣọ́ ẹnu ibodè kí a lè pa ọjọ́ ìsinmi mọ́.Tún rántíì mi fún èyí, Ọlọ́run mi, kí o sì fi àánú un rẹ hàn fún mi gẹ́gẹ́ bí i títóbi ìfẹ́ẹ̀ rẹ.

23. Ní ọjọ́ wọ̀n ọn nì, mo rí àwọn ọkùnrin Júdà tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin láti Áṣídódù, Ámónì àti Móábù.

24. Ìdajì àwọn ọmọ wọn ń sọ èdè Áṣídódù tàbí èdè ọ̀kan lára àwọn ènìyàn mìíràn tó kù, wọn kò sì mọ bí a ṣe ń ṣọ èdè Júdà.

25. Mo bá wọn wí mo sì gégùn-ún lé wọn lórí. Mo lu àwọn ènìyàn díẹ̀ nínú un wọn mo sì fa irun oríi wọn tu. Mo mú kí wọn búra ní orúkọ Ọlọ́run, kí wọn wí pé, “Ẹ̀yin kì yóò fi àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin yín ní ìyàwó tàbí fún ẹ̀yin tìkáara yín.

26. Kìí ha á ṣe àwọn ìgbéyàwó bí irú èyí ni ọba Sólómónì fi dá ẹ̀ṣẹ̀? Láàrin àwọn orìlẹ̀ èdè, kò sí ọba kan bí i tirẹ̀. Ọlọ́run rẹ̀ féràn rẹ̀, Ọlọ́run sì fi jẹ ọba lóríi gbogbo Ísírẹ́lì, ṣùgbọ́n àwọn obìnrin àjòjì ti sọ ọ́ sínú òfin ẹ̀ṣẹ̀.

27. Ǹjẹ́ ó ha yẹ kí àwa tún gbọ́ báyìí pé ẹ̀yin náà tún ń ṣe àwọn nǹkan tí ó burú jọjọ wọ̀nyí tí ẹ sì ń ṣe aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjòjì?”

28. Ọ̀kan lára àwọn ọmọ Jóíádà, ọmọ Élíásíbù olórí àlùfáà jẹ́ àna (o fẹ ọmọbìnrin) Ṣáńbálátì ará a Hórónì. Mo sì lé e jáde kúrò lọ́dọ̀ mi.

Ka pipe ipin Nehemáyà 13