Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 13:46-53 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

46. Gbogbo ìgbà tí àrùn náà bá wà ní ara rẹ̀; aláìmọ́ ni: kí ó máa dá gbé. Kí ó máa gbé lẹ́yìn ibùdó.

47. “Bí àrùn ẹ̀tẹ̀ bá ba aṣọ kan jẹ́ yálà aṣọ onírun àgùtàn tàbí aṣọ funfun.

48. Ìbáà ṣe títa tàbí híhun tí ó jẹ́ aṣọ funfun tàbí irun àgùtàn, bóyá àwọ̀ tàbí ohun tí a fi àwọ̀ ṣe.

49. Bí ìbàjẹ́ ara aṣọ: ìbáà ṣe awọ, irun àgùtàn, aṣọ títa, aṣọ híhun tàbí ohun tí a fi awọ ṣe bá di aláwọ̀ ewé tàbí kí ó pupa: èyí jẹ́ ẹ̀tẹ̀ tí ń ràn ká. Ẹ gbọdọ̀ fi hàn fún àlùfáà.

50. Àlùfáà yóò yẹ ẹ̀tẹ̀ náà wò, yóò sì pa gbogbo ohun tí ẹ̀tẹ̀ náà ti ràn mọ́ fún ọjọ́ méje.

51. Ní ọjọ́ keje kí ó yẹ̀ ẹ́ wò bí àrùn ẹ̀tẹ̀ náà bá ràn ká ara aṣọ tàbí irun àgùtàn, aṣọ híhun tàbí awọ, bí ó ti wù kí ó wúlò tó, ẹ̀tẹ̀ apanirun ni èyí jẹ́, irú ohun bẹ́ẹ̀ kò mọ́.

52. Ó gbọdọ̀ sun aṣọ náà tàbí irun àgùtàn náà, aṣọ híhun náà tàbí awọ náà ti ó ni ìbàjẹ́ kan lára rẹ̀ ni iná torí pé ẹ̀tẹ̀ tí í pa ni run ni. Gbogbo nǹkan náà ni ẹ gbọdọ̀ sun ní iná.

53. “Ṣùgbọ́n bí àlùfáà bá yẹ̀ ẹ́ wò tí ẹ̀tẹ̀ náà kò ràn ká ara aṣọ náà yálà aṣọ títa, aṣọ híhun tàbí aláwọ.

Ka pipe ipin Léfítíkù 13