Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóẹ́lì 1:6-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Nítorí orílẹ̀ èdè kan ti sígun sí ilẹ̀ mìírànó ní agbára púpọ̀, kò sì ní òǹkà;ó ní eyín kìnnìúnó sì ní èrìgì abo kìnnìún.

7. Ó ti pa àjàrà mi run,ó sì ti ya ẹ̀ka igi ọ̀pọ̀tọ́ mi kúrò,ó ti bò èèpo rẹ̀ jálẹ̀, ó sì sọ ọ́ nù;àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ni a sì sọ di fun-fun.

8. Ẹ pohùnréré ẹkún bí wúndíátí a fi aṣọ ọ̀fọ̀ dí ni àmúre, nítorí ọkọ ìgbà èwe rẹ̀.

9. A ké ọrẹ jíjẹ́ àti ọrẹ mímú kúròní ilé Olúwa;àwọn àlùfáà ń ṣọ̀fọ̀, àwọnìrànṣẹ́ Olúwa,

10. Oko di ìgboro, ilẹ̀ ń sọ̀fọ̀ nítorí,a fi ọkà ṣòfò:ọtí wáìnì tuntún gbé, òróró ń bùṣe.

11. Kí ojú kí ó tì yín, ẹ̀yin àgbẹ̀;ẹ pohùn réré ẹkún ẹ̀yin olùtọ́jú àjàrà,nítorí àlìkámà àti nítorí ọkà báálì;nítorí ìkórè oko ṣègbé.

12. Àjàrà gbẹ, igi ọ̀pọ̀tọ́ sì rọ̀ dànù;igi pómégánátì, igi ọ̀pẹ pẹ̀lú,àti igi ápíílì, gbogbo igi igbó ni o rọ:Nítorí náà ayọ̀ ọmọ ènìyàn gbẹ kúrò lọ́dọ̀ wọn

13. Ẹ di ara yín ni àmùrè,sí pohùn réré ẹkún ẹyín àlùfáà:ẹ pohùn réré ẹkún, ẹyín ìránṣẹ́ pẹpẹ:ẹ wá, fi gbogbo òru dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀,ẹ̀yin ìrànsẹ́ Ọlọ́run mi: nítorí tí a dá ọrẹ jíjẹ àti ọrẹmímú dúró ní ilé Ọlọ́run un yín.

14. Ẹ yà ààwẹ̀ kan sí mímọ́,ẹ pe àjọ kan tí o ní ìrònú,ẹ pe àwọn àgbà,àti gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náàjọ sí ilé Olúwa Ọlọ́run yín,kí ẹ sí képe Olúwa

15. A! Fún ọjọ́ náà,nítorí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀,yóò de bí ìparun láti ọwọ́ Olódùmare.

16. A kò ha ké oúnjẹ kúrò níwájúojú wá yìí,ayọ̀ àti inú dídùn kúrò nínú iléỌlọ́run wá?

Ka pipe ipin Jóẹ́lì 1