Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóẹ́lì 1:3-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ẹ sọ ọ́ fún àwọn ọmọ yín,ki àwọn ọmọ yín sọ fún àwọn ọmọ wọn,ki àwọn ọmọ wọn sọ fún àwọn ìran mìíràn.

4. Èyí tí eṣú tí agénijẹ jẹ kùní ọ̀wọ́ eṣú jẹÈyí tí ọ̀wọ́ eṣú jẹ kùní eṣú tata jẹÈyí tí eṣú tata jẹ kùni eṣú apanirun mìíràn jẹ

5. Ẹ jí gbogbo ẹ̀yín ọ̀mùtí kí ẹ sì ṣunkúnẹ pohùnréré ẹkún gbogbo ẹ̀yinọ̀mu-wáìnì; ẹ pohùnréré ẹkún nítorí wáìnì tuntunnítorí a gbà á kúrò lẹ́nu yín.

6. Nítorí orílẹ̀ èdè kan ti sígun sí ilẹ̀ mìírànó ní agbára púpọ̀, kò sì ní òǹkà;ó ní eyín kìnnìúnó sì ní èrìgì abo kìnnìún.

7. Ó ti pa àjàrà mi run,ó sì ti ya ẹ̀ka igi ọ̀pọ̀tọ́ mi kúrò,ó ti bò èèpo rẹ̀ jálẹ̀, ó sì sọ ọ́ nù;àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ni a sì sọ di fun-fun.

8. Ẹ pohùnréré ẹkún bí wúndíátí a fi aṣọ ọ̀fọ̀ dí ni àmúre, nítorí ọkọ ìgbà èwe rẹ̀.

9. A ké ọrẹ jíjẹ́ àti ọrẹ mímú kúròní ilé Olúwa;àwọn àlùfáà ń ṣọ̀fọ̀, àwọnìrànṣẹ́ Olúwa,

10. Oko di ìgboro, ilẹ̀ ń sọ̀fọ̀ nítorí,a fi ọkà ṣòfò:ọtí wáìnì tuntún gbé, òróró ń bùṣe.

11. Kí ojú kí ó tì yín, ẹ̀yin àgbẹ̀;ẹ pohùn réré ẹkún ẹ̀yin olùtọ́jú àjàrà,nítorí àlìkámà àti nítorí ọkà báálì;nítorí ìkórè oko ṣègbé.

12. Àjàrà gbẹ, igi ọ̀pọ̀tọ́ sì rọ̀ dànù;igi pómégánátì, igi ọ̀pẹ pẹ̀lú,àti igi ápíílì, gbogbo igi igbó ni o rọ:Nítorí náà ayọ̀ ọmọ ènìyàn gbẹ kúrò lọ́dọ̀ wọn

Ka pipe ipin Jóẹ́lì 1