Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóẹ́lì 1:12-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Àjàrà gbẹ, igi ọ̀pọ̀tọ́ sì rọ̀ dànù;igi pómégánátì, igi ọ̀pẹ pẹ̀lú,àti igi ápíílì, gbogbo igi igbó ni o rọ:Nítorí náà ayọ̀ ọmọ ènìyàn gbẹ kúrò lọ́dọ̀ wọn

13. Ẹ di ara yín ni àmùrè,sí pohùn réré ẹkún ẹyín àlùfáà:ẹ pohùn réré ẹkún, ẹyín ìránṣẹ́ pẹpẹ:ẹ wá, fi gbogbo òru dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀,ẹ̀yin ìrànsẹ́ Ọlọ́run mi: nítorí tí a dá ọrẹ jíjẹ àti ọrẹmímú dúró ní ilé Ọlọ́run un yín.

14. Ẹ yà ààwẹ̀ kan sí mímọ́,ẹ pe àjọ kan tí o ní ìrònú,ẹ pe àwọn àgbà,àti gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náàjọ sí ilé Olúwa Ọlọ́run yín,kí ẹ sí képe Olúwa

15. A! Fún ọjọ́ náà,nítorí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀,yóò de bí ìparun láti ọwọ́ Olódùmare.

16. A kò ha ké oúnjẹ kúrò níwájúojú wá yìí,ayọ̀ àti inú dídùn kúrò nínú iléỌlọ́run wá?

17. Irúgbìn bàjẹ́ nínú ebè wọn,a sọ àká di ahoro, a wó àká palẹ̀;nítorí tí a mú ọkà rọ.

Ka pipe ipin Jóẹ́lì 1