Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 5:14-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run alágbára wí:“Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí;Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná,àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.

15. Áà, ẹ̀yin ilé Ísírẹ́lì,” ni Olúwa wí,“Èmi yóò mú kí orílẹ̀ èdè láti ọ̀nà jínjìn dìde sí i yínOrílẹ̀ èdè ìgbàanì àti alágbára nìàwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀,tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.

16. Àpò ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a sígbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.

17. Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ,àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin,wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ,wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ.Pẹ̀lú idà ni wọn ó runìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.”

18. “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátapáta.

19. Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin Ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsìnyìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe ti yín.’

20. “Kéde èyí fún ilé Jákọ́bù,kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Júdà.

21. Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aláìlóye àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn,tí ó lójú ti kò fi rírantí ó létí ti kò fi gbọ́ran.

22. Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí.“Kò ha yẹ kí èyin ó wárìrì níwájú mi bí?Mo fi yanrìn pààlà òkun,èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé.Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀;wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.

23. Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀,wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.

24. Wọn kò sọ fún ara wọn pé,‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa,ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀,tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédéé.’

25. Àìṣedéedée yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò,ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.

26. “Láàrin ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wàtí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ,àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.

27. Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ,ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn.Wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,

28. Wọ́n sanra wọ́n sì dán.Ìwà búburú wọn kò sì lópin;wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀.Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.

29. Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?”ni Olúwa wí.“Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara milára orílẹ̀ èdè bí èyí bí?

30. “Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtarati ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.

31. Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké,àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn,àwọn ènìyàn mi sì nífẹ̀ẹ́ sí èyí,kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?

Ka pipe ipin Jeremáyà 5