Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 38:18-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Ṣùgbọ́n tí o kò bá jọ̀wọ́ ara rẹ fún àwọn ìjòyè Ọba Bábílónì, a ó fa ìlú yìí lé ọwọ́ àwọn Bábílónì. Wọn yóò sì fi ina sun-un, ìwọ gan-an kò ní le sá mọ́ wọn lọ́wọ́.’ ”

19. Ọba Sedekáyà sọ fún Jeremáyà pé, “Mò ń bẹ̀rù àwọn Júù tó ti sálọ sí ilẹ̀ Bábílónì, nítorí pé àwọn ará Bábílónì lè fà mí lé wọn lọ́wọ́ láti fìyà jẹ mí.”

20. Jeremáyà sì dáhùn wí pé, “Wọn kò ní fi ọ́ lé e lọ́wọ́. Pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́ nípa ṣíṣe ohun tí mo sọ fún ọ; yóò sì dára fún ọ, ẹ̀mí rẹ yóò sì wà.

21. Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá kọ̀ láti jọ̀wọ́ ara rẹ, èyí ni ohun tí Olúwa ti fi hàn mí:

22. Gbogbo àwọn obìnrin tó kù ní ààfin Ọba Júdà ni wọn yóò kó jáde fún àwọn ìjòyè Ọba Bábílónì. Àwọn obìnrin náà yóò sì sọ fún ọ pé:“ ‘Àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tàn ọ́ jẹ,wọ́n sì borí rẹ.Ẹsẹ̀ rẹ rì sínú orọ̀fọ̀;àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti fi ọ́ sílẹ̀.’

23. “Wọn yóò kó àwọn ìyàwó àti ọmọ rẹ wá sí Bábílónì. Ìwọ gan-an kò ní bọ́ níbẹ̀, Ọba Bábílónì yóò mú ọ, wọn yóò sì jó ìlú yìí kanlẹ̀.”

Ka pipe ipin Jeremáyà 38