Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 2:6-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà tí ó mú wọn,jáde láti ilẹ̀ Éjíbítì, tí ó mú wala ihà já, tí ó mu wọn la àárin àwọnaṣálẹ̀ àti òkè láàrin ìyàngbẹ ilẹ̀àti òkùnkùn wá ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́nikò ti rìnrìn-àjò, tí ẹníkẹ́ni kò sì gbé?’

7. Mo mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá láti máajẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀, ẹ̀yin sì wá, ẹ sìba ilẹ̀ náà jẹ́, ẹ sì mú àwọnohun ogún mi di ohun ìríra.

8. Àlùfáà kò bèèrè wí pé níbo ni Olúwa wà? Àwọn tí ń ṣiṣẹ́pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí, àwọnolórí wọn sì gbógun sí mi,àwọn wòlíì sì ń sọ tẹ́lẹ̀ nípaòrìṣà báálì, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọnòrìṣà yẹpẹrẹ.

9. “Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ́kan síi,”ni Olúwa wí.“Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ

10. Rékọjá sí ẹkùn kan kítímì, kí osì wò ó, ránṣẹ́ sí kéda, kí o sìwò ó dáradára, wò ó kí ẹ sìwò ó bí irú nǹkan báyìí báwà níbẹ̀ rí?

11. Orílẹ̀ èdè kan há á pa Ọlọ́run rẹ̀ dà?(Síbẹ̀, wọn kì í ṣe iṣẹ́ Ọlọ́run)àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.

12. Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́sẹ̀ méjìkí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,”ni Olúwa wí.

13. “Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́sẹ̀, méjìWọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmiorísun omi ìyè, wọ́n sì tiwọ àmù, àmù fífọ́ tí kò lègba omi dúró.

14. Ísírẹ́lì há á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ẹrú nípa ìbí? Kí ló há adé tí ó fi di ìkógun?

15. Àwọn kìnnìún ké ramúramúwọ́n sì ń bú mọ́ wọnwọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfòÌlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sìti di ìkọ̀sílẹ̀.

16. Bákan náà, àwọn ọkùnrinMémífísì àti Táfánésìwọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.

17. Ẹ̀yin kò há a ti fa èyí sóríara yín nípa kíkọ Ọlọ́run sílẹ̀nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?

18. Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Éjíbítìláti lọ mu omi ní Síhórì?Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Àsíríàláti lọ mu omi ni odò Yúfúrátè náà

19. Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yínÌpàdàṣẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wímọ̀ kí o sì ríi wí pé ibi àtiohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹnígbà tí o ti kọ Ọlọ́run ọmọogun sílẹ̀, ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,”ni Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ ogun wí.

20. “Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgàrẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’Lóòtọ́, lórí gbogbo òkè gíga niàti lábẹ́ igi tí ó tàn kálẹ̀ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.

21. Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bíàjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá,Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí midi àjàrà búburú àti aláìmọ́?

22. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódàtí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹàbàwọ́n àìṣedéédéé rẹ sì ń bọ̀ níwájú mi,”ni Olúwa Àwọn ọmọ ogun wí.

23. “Báwo ni o ṣe le lọ sọ pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́;Èmi kò ṣáà tẹ̀lé àwọn Báálì’?Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì;wo ohun tí o ṣe.Ìwọ jẹ́ abo ìbákasíẹ̀tí ń sá sí ìhín sọ́hùn ún.

24. Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́ tí ń gbé ihàtí ń fa ẹ̀fúùfù nínú ìfẹ́ inú rẹ̀ta ni ó le è mu dúró ní àkókò rẹ̀?Kí gbogbo àwọn ọkùnrin tí ílé e má ṣe dára wọn lágaranítorí wọn ó ò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.

Ka pipe ipin Jeremáyà 2