Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 2:20-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. “Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgàrẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’Lóòtọ́, lórí gbogbo òkè gíga niàti lábẹ́ igi tí ó tàn kálẹ̀ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.

21. Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bíàjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá,Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí midi àjàrà búburú àti aláìmọ́?

22. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódàtí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹàbàwọ́n àìṣedéédéé rẹ sì ń bọ̀ níwájú mi,”ni Olúwa Àwọn ọmọ ogun wí.

23. “Báwo ni o ṣe le lọ sọ pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́;Èmi kò ṣáà tẹ̀lé àwọn Báálì’?Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì;wo ohun tí o ṣe.Ìwọ jẹ́ abo ìbákasíẹ̀tí ń sá sí ìhín sọ́hùn ún.

24. Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́ tí ń gbé ihàtí ń fa ẹ̀fúùfù nínú ìfẹ́ inú rẹ̀ta ni ó le è mu dúró ní àkókò rẹ̀?Kí gbogbo àwọn ọkùnrin tí ílé e má ṣe dára wọn lágaranítorí wọn ó ò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.

25. Má ṣe sáré títí ẹṣẹ̀ yín yóò fi wà ní ìhòòhò,tí ahọ́n yín yóò sì gbẹ.Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Kò nílò!Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì,èmi yóò sì lépa wọn lọ.’

26. “Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójú ti olènígbà tí a bá mú u,bẹ́ẹ̀ náà ni ilé Ísírẹ́lìyóò gba, àwọn ìjòyè wọn,àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.

27. Wọn sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni bàbá mi,’àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi, wọn kò kọojú sí mi ṣíbẹ̀ nígbà tí wọ́nbá wà nínú ìṣòro, wọn yóòwí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’

28. Níbo wá ni àwọn Ọlọ́run (kékeré) tíẹ ṣe fúnra yín há a wà?Jẹ́ kí wọn wá kí wọn sìgbà yín nígbà tí ẹ báwà nínú ìṣòro! Nítorí péẹ̀yin ní àwọn Ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́bí ẹ ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Júdà.

29. “Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí?Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,”ni Olúwa wí.

30. “Nínú aṣán mo fìyà jẹ àwọnènìyàn yín, wọn kò sì gbaìbáwí, idà yín ti pa àwọnwòlíì yín run, gẹ́gẹ́ bíkìnnìún tí ń bú ramúramù.

Ka pipe ipin Jeremáyà 2