Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 20:8-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. “ ‘Ṣùgbọ́n wọn sọ̀tẹ̀ sí mi wọn kò sì gbọ́ràn, wọn kò gbé àwòrán ìríra tí wọ́n dojú kọ kúrò níwájú wọn bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si kọ̀ àwọn òrìṣà Éjíbítì sílẹ̀, torí náà mo sọ pé ń ó tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí, ń ó sì jẹ kí ìbínú mi sẹ̀ lórí wọn ní ilẹ̀ Éjíbítì.

9. Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní jẹ́ kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀ èdè tí wọn ń gbé láàrin wọn, lójú àwọn ẹni tí mo ti fi ara hàn fún ara Ísírẹ́lì nípa mímú wọn jáde ní ilẹ̀ Éjíbítì.

10. Nítorí náà, mo mú wọn jáde ní ilẹ̀ Éjíbítì mo sì mú wọn wá sínú ihà.

11. Mo sì fún wọn ni òfin mi, mo sì fi àwọn òfin mi hàn wọ́n; nítori pé ẹni tó bá ṣe wọ́n yóò yè nípa wọn.

12. Bẹ́ẹ̀ ni mo fún wọn ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí àmì láàrin àwọn àti èmi, kí wọn lè mọ̀ pé èmi ni Olúwa tó sọ wọn di mímọ́.

13. “ ‘Síbẹ̀; ilé Ísírẹ́lì sọ̀tẹ̀ sí mí nínú ihà. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sì kọ àwọn òfin mi sílẹ̀-bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá pa á mọ́ yóò yè è nínú rẹ̀. Wọn sì sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́ lọ́pọ̀lọpọ̀. Nítorí náà, mo sọ pé ń ó tú ìbínú gbígbóná mi sórí wọn, ń ó sì pa wọ́n run nínú ihà.

14. Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní mú kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀ èdè tí mo kó wọn jáde lójú wọn.

15. Nítorí náà, mo tún gbọ́wọ́ mi sókè jẹ́jẹ̀ẹ́ fún wọn nínú ihà pé ń kò ní i mú wọn dé ilẹ̀ tí mo fi fún wọn—ilẹ̀ tí ń ṣàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrin àwọn ilẹ̀ yòókù.

16. Nítorí pé wọn kọ òfin mi sílẹ̀, wọn kò sì tẹ̀lé àsẹ mi, wọn sọ ọjọ́ ìsinmi mi dí aláìmọ́. Nítorí pé tọkàntọkàn ni wọn ń tẹ̀lé òrìṣà wọn.

17. Síbẹ̀síbẹ̀ mo wò wọ́n pẹ̀lú àánú, ń kò sì pa wọ́n run tàbí kí òpin dé bá wọn nínú ihà.

18. Ṣùgbọ́n mo sọ fún àwọn ọmọ wọn nínú ihà pé, “Ẹ má ṣe rìn ní ìlànà àwọn baba yín tàbí kí ẹ pa òfin wọn mọ́ tàbí kí ẹ bara yín jẹ́ pẹ̀lú òrìṣà wọn.

19. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ó sì pa òfin mi mọ́.

20. Ẹ ya ọjọ́ ìsinmi mi sí mímọ́ kí ó lè jẹ́ àmì láàrin wa: ki ẹ lè mọ̀ pé èmi ní Olúwa Ọlọ́run yín.”

21. “ ‘Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ náà ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn kò sì pa òfin mí mọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá tẹ̀lé àwọn òfin yìí, yóò yè nínú rẹ̀, wọ́n sì tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Nítorí náà, mo sọ pé ń ó tú ìbínú mi lórí wọn N ó sì mú kí ibínú gbígbóná mi wá sórí wọn ni ihà.

22. Síbẹ̀síbẹ̀ mo dáwọ́ dúró, nitori orúkọ mi mo sì ṣe ohun tí kò ní bá orúkọ mi jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀ èdè ti mo kó wọn jáde lójú wọn.

23. Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú ọwọ ti mo gbé sókè, mo jẹ́jẹ̀ẹ́ fún wọn nínú ihà pé n ó tú wọn ka sì àárin àwọn orílẹ̀ èdè, ń ó sì fọ́n wọn káàkiri ilẹ̀ gbogbo,

24. nítorí pé wọn kò pa òfin mí mọ́, wọn sì tún kọ àsẹ mi sílẹ̀, wọn tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Ọkàn wọn sì dúró ṣinṣin sọ́dọ̀ òrìṣà baba wọn.

25. Èmi náà sì fi wọn fún ìlànà tí kò dára àti òfin tí wọn kò le e yè nípa rẹ̀;

26. Mo jẹ́ kí ó sọ wọn di aláìmọ́ nípa ẹ̀bùn-nipa fífi àkọ́bí ọmọ wọn rú ẹbọ sísun àkọ́bí wọn la iná kọjá, kí ń lè kó ìpayà bá wọn, kí wọn le mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 20