Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hósíà 9:8-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Wòlíì, papọ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run,ni olùṣọ́ ọ Éfúráímù.Ṣíbẹ̀ ìdẹ̀kùn dúró dè é ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀àti ìkórìíra ní ilé Ọlọ́run rẹ̀

9. Wọ́n ti gbilẹ̀ nínú ìwà ìbàjẹ́gẹ́gẹ́ bí i ọjọ́ GíbíàỌlọ́run yóò rántí ìwà búburú wọnyóò sì jẹ wọ́n níyà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

10. “Nígbà tí mo rí Ísírẹ́lì,Ó dàbí ìgbà tí ènìyàn rí èso àjàrà ní ilẹ̀ aṣálẹ̀Nígbà tí mo rí àwọn baba yín.Ó dàbí ìgbà tí ènìyàn rí àkọ́so èso lórí igi ọ̀pọ̀tọ́ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n dé ọ̀dọ̀ Baali-PéórìWọ́n yà wọn sọ́tọ̀ fún òrìṣà tó ń mú ìtìjú bá niwọ́n di aláìmọ́ bí ohun tí wọ́n fẹ́ràn.

11. Ògo Éfúráímù yóò fò lọ bí ẹyẹkò ní sí ìfẹ́rakù, ìlóyún àti ìbímọ.

12. Bí wọ́n tilẹ̀ tọ́ ọmọ dàgbà.Èmi yóò mú wọn ṣọ̀fọ̀ lórí gbogbo wọnÈgbé ni fún wọn,nígbà tí mo yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn!

13. Mo rí Éfúráímù bí ìlú Tírúsìtí a tẹ̀dó sí ibi dáradáraṣùgbọ́n Éfúráímù yóò kó àwọnọmọ rẹ̀ jáde fún àwọn apànìyàn.”

14. Fún wọn, Olúwa!Kí ni ìwọ yóò fún wọn?Fún wọn ní inú tí ń ba oyún jẹ́àti ọyàn gbígbẹ.

15. “Nítorí gbogbo ìwà búburú tí wọ́n hù ní GílígálìMo kórìírà wọn níbẹ̀,Nítorí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.Èmi yóò lé wọn jáde ní ilé miÈmi kò ní ní ìfẹ́ wọn mọ́ọlọ̀tẹ̀ ni gbogbo olórí wọn.

Ka pipe ipin Hósíà 9