Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hósíà 1:9-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Olúwa sì sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-ámì, (kì í ṣe ènìyàn mi) nítorí pé ẹ kì í ṣe ènìyàn mi, èmi náà kì í sì í ṣe Ọlọ́run yín.

10. “Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Ísírẹ́lì yóò pọ̀ bíi iyanrìn etí òkun tí a kò le wọ̀n, tí a kò sì le è kà, yóò síṣe. Ní ibi tí wọ́n ti sọ fún wọn pé. ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó ti máa pè wọ́n ní ‘ọmọ Ọlọ́run alààyè.’

11. Àwọn ènìyàn Júdà àti àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì yóò para pọ̀, wọn yóò sì yan olórí kan tí yóò jáde láti ilẹ̀ náà, nítorí pé ọjọ́ ńlá ni ọjọ́ Jésírẹ́lì yóò jẹ́.

Ka pipe ipin Hósíà 1