Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hósíà 1:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Hósíà ọmọ Béérì wá ní àkókò ìjọba Ùsáyà, Jótamù, Áhásì àti Heṣekáyà; àwọn ọba Júdà àti ní àkókò ọba Jéróbóámù ọmọ Jóásì ní Ísírẹ́lì:

2. Nígbà tí Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀ láti ẹnu Hósíà, Olúwa wí fún un pé, “Lọ, fẹ́ àgbèrè obìnrin kan fún araa rẹ, kí ó sì bí ọmọ àgbèrè fún ọ nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin mìíràn, nítorí ilẹ̀ ti ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè púpọ̀ nípa yíyapa kúrò lọ́dọ̀ Olúwa.”

3. Nígbà náà ni ó sì lọ, ó sì fẹ́ Gómérì ọmọbìnrin Díbíláémù, ọmọbìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un.

4. Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Hósíà pé, “Pe orúkọ ọmọ náà ní Jésírẹ́lì, nítorí pé láìpẹ́ ni èmi yóò jẹ ìdílé Jéhù ní ìyà fún ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn tó pa ní ìpakúpa ní Jésírẹ́lì, Èmi yóò sì mú ìjọba Ísírẹ́lì wá sí òpin.

5. Ní ọjọ́ náà ni Èmi yóò sẹ́ ọrun Ísírẹ́lì ní àfonífojì Jésírẹ́lì.”

Ka pipe ipin Hósíà 1