Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 5:13-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, kí ẹ ṣe iṣẹ́ ẹ yín pátapáta

14. Ṣùgbọ́n ọjọ́ kéje ni ọjọ́ ìsinmi sí Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà yálà ìwọ tàbí àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin tàbí àwọn ọmọ rẹ obìnrin, tàbí àwọn ẹrú ọkùnrin tàbí ẹrú obìnrin yín tàbí màlúù yín, tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ yín, tàbí èyíkéyìí nínú àwọn ẹran yín, tàbí àwọn àlejò yín, kí àwọn ẹrú-kùnrin àti ẹrú-bìnrin yín le è sinmi, bí i yín.

15. Ẹ rántí pé ẹ ti jẹ́ ẹrú ní Éjíbítì rí, àti pé Olúwa Ọlọ́run yín yọ yín kúrò níbẹ̀ pẹ̀lú agbára ńlá, àti nína ọwọ́ rẹ̀. Torí èyí ni Olúwa Ọlọ́run yín ṣe pàṣẹ fún un yín láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́.

16. “Bọ̀wọ̀ fún baba àti ìyáà rẹ, bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín, kí ẹ ba à le è pẹ́ láyé, àti kí ó bá à lè dára fún un yín ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín.

17. “Má ṣe pànìyàn.

18. “Má ṣe ṣe panṣágà.

19. “Má ṣe jalè.

20. “Má ṣe jẹ́rìí èké sí aládùúgbò rẹ

21. “Má ṣe ṣe ojúkòkòrò sí aya aládúgbò rẹ, má ṣe ṣe ojúkòkòrò sí ilé tàbí ilẹ̀ alábágbé rẹ, sí ẹrúkùnrin tàbí ẹrúbìnrin rẹ̀, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, tàbí ohunkóhun tí í ṣe ti aládúgbò rẹ.”

22. Wọ̀nyí ni àwọn àṣẹ Olúwa tí a kéde rẹ̀ sí gbogbo ìpéjọpọ̀ ọ yín, níbẹ̀ ní orí òkè, láàrin iná, ìkùukù àti òkùnkùn biribiri: Kò sì fi ohunkóhun kún un mọ́. Ó sì kọ wọ́n sínú sílétì méjì, Ó sì fi wọ́n lé mi lọ́wọ́.

23. Nígbà tí ẹ gbóhùn láti inú òkùnkùn wá, nígbà tí iná náà ń yọná lala, àwọn aṣáájú ẹ̀yà a yín àti àwọn alàgbà a yín tọ̀ mí wá.

24. Ẹ sì sọ pé, “Olúwa Ọlọ́run wa ti fi ògo rẹ̀ hàn wá, àti títóbi rẹ̀ a sì ti gbóhùn rẹ̀ láti àárin iná wá. A ti rí i lónìí pé, ènìyàn sì lè wà láàyè lẹ́yìn tí Olúwa bá bá a sọ̀rọ̀.

25. Ṣùgbọ́n èéṣe tí àwa yóò fi kú? Iná ńlá yìí yóò jó wa run, bí àwa bá sì tún gbọ́ ohun Olúwa Ọlọ́run wa, àwa ó kú.

26. Ta ni nínú ẹlẹ́ran ara tí ó ti gbọ́ ohun Olúwa Ọlọ́run láti inú iná rí, bí àwa ti gbọ́ ọ, tí a sì wà láyé?

Ka pipe ipin Deutarónómì 5