Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Dáníẹ́lì 1:11-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Nígbà náà ni Dáníẹ́lì sọ fún olùṣọ́ tí olórí àwọn ìwẹ̀fà yàn lórí i Dáníẹ́lì, Hananiáyà, Mísáẹ́lì àti Ásáríyà pé,

12. Jọ̀wọ́ dán àwa ìránṣẹ́ rẹ wò fún ọjọ́ mẹ́wàá: Má ṣe fún wa ní ohun kankan, àfi ẹ̀fọ́ láti jẹ àti omi láti mu.

13. Nígbà náà ni kí o fi ìrísí i wa wé ti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba, kí o sì ṣe àwa ìránṣẹ́ rẹ ní ìbámu pẹ̀lú u bí o bá ṣe rí i sí.

14. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì gbà láti dán wọn wò fún ọjọ́ mẹ́wàá.

15. Lẹ́yìn ọjọ́ kẹwàá ara wọn le, wọ́n sì sanra ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí wọ́n ń jẹ oúnjẹ ọba lọ.

16. Bẹ́ẹ̀ ni olùṣọ́ mú oúnjẹ àdídùn àti wáìnì tí ó yẹ kí wọ́n mu kúrò, ó sì fún wọn ní ẹ̀fọ́ dípò rẹ̀.

17. Ọlọ́run fún àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí ní ìmọ̀ àti òyé nínú un gbogbo onírúurú ìwé àti ẹ̀kọ́ ọ wọn: Dáníẹ́lì sì ní òyé ìran àti àlá ní oríṣìíríṣìí.

18. Ní òpín ìgbà tí ọba dá, pé kí a mú wọn wá sínú ààfin, olórí àwọn ìwẹ̀fà mú wọn wá ṣíwájú ọba Nebukadinésárì.

19. Ọba sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì rí i pé kò sí ẹni tí ó dàbí i Dáníẹ́lì, Hananíáyà, Míṣáẹ́lì àti Ásáríyà; Nítorí náà wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣe iṣẹ́ ọba.

20. Nínú un gbogbo ọ̀ràn, ọgbọ́n àti òyé tí ọba ń bèrè lọ́wọ́ ọ wọn, ó rí i pé wọ́n sàn ní ìlọ́po mẹ́wàá ju gbogbo àwọn amòye àti ọlọ́gbọn tí ó wà ní gbogbo ìjọba rẹ̀.

21. Dáníẹ́lì sì wà níbẹ̀ títí di ọdún kìn-ín-ní ọba Kírúsì.

Ka pipe ipin Dáníẹ́lì 1