Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 66:3-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fi akọ màlúù rúbọó dàbí ẹni tí ó pa ènìyàn kanàti ẹni tí ó bá fi ọ̀dọ́ àgùntàn kan tọrẹ,dàbí ẹni tí ó kán ajá kan lọ́rùn;ẹnikẹ́ni tí ó bá fi irúgbin oníhóró tọrẹdàbí ẹni tí ó mú ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ wá,ẹni tí ó bá sì ṣun tùràrí ìrántí,dàbí ẹni tí ó sin ère òrìṣà.Wọ́n ti yan ipa ọ̀nà tiwọn,ọkàn wọn pẹ̀lú sì láyọ̀ nínú ohun ìríra wọn;

4. Fún ìdí èyí ni èmi pẹ̀lú yóò ṣe fi ọwọ́ líle mú wọnn ó sì mú ohun tí wọ́n bẹ̀rù rẹ̀ wá sórí wọn.Nítorí nígbà tí mo pè, kò sí ẹni tí ó dáhùn,nígbà tí mo sọ̀rọ̀, ẹnikẹ́ni kò tẹ́tísílẹ̀.Wọ́n ṣe ohun búburú ní ojú miwọ́n sì yan ohun tí mo kóríìra rẹ̀.”

5. Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,Ẹ̀yin tí ẹ ń wárìrì nípaṣẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀:“Àwọn arákùnrin yín tí wọ́n kóríra yín,tí wọ́n ta yín nù nítorí orúkọ mi, wí pé,‘Jẹ́ kí a yin Olúwa lógo,kí a le rí ayọ̀ yín!’Ṣùgbọ́n àwọn ni ojú yóò tì.

6. Gbọ́ rògbòdìyàn n nì láti ìlú wá,gbọ́ ariwo náà láti tẹ́ḿpìlì wá!Ariwo tí Olúwa ní í ṣetí ó ń san án fún àwọn ọ̀ta rẹ̀ ohuntí ó tọ́ sí wọn.

7. “Kí ó tó lọ sí ìrọbí,ó ti bímọ;kí ó tó di pé ìrora dé bá a,ó ti bí ọmọkùnrin.

8. Ta ni ó ti gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí?Ta ni ó ti rí irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí?Ǹjẹ́ a le bí orílẹ̀ èdè kan níjọ́ kantàbí kí orílẹ̀ èdè lalẹ̀hù ní ìṣẹ́jú kan?Síbẹ̀síbẹ̀ Ṣíhónì bẹ̀rẹ̀ rírọbí tàìrọbíbẹ́ẹ̀ ni ó sì bí àwọn ọmọ rẹ̀.

9. Ǹjẹ́ èmi a ha máa mú wá sí ìrọ́bíkí èmi má sì mú ni bí?” ni Olúwa wí.“Ǹjẹ́ èmi a ha máa ṣé ilé ọmọnígbà tí mo ń mú ìbí wá?” ni Ọlọ́run yín wí.

10. “Ẹ bá Jérúsálẹ́mù yọ̀ kí inú yín kí ó sì dùn sí i,gbogbo ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn rẹ̀;ẹ yọ̀ gidigidi pẹ̀lú rẹ̀,gbogbo ẹ̀yin tí ó ti kẹ́dùn fún un.

11. Nítorí pé ẹ̀yin yóò mu ẹ o sì ní ìtẹ́lọ́rùnnínú ọmú rẹ̀ tí ó túnilára;Ẹ̀yin yóò mu àmuyóẹ ó sì gbádùn nínú à-kún-wọ́-sílẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ rẹ̀.”

12. Nítorí ohun tí Olúwa wí nìyìí:“Èmi yóò fún un ní àlàáfíà gẹ́gẹ́ bí odòàti ọrọ̀ orílẹ̀ èdè gẹ́gẹ́ bí ìṣàn omi;ẹ̀yin yóò mu ọmú, a ó sì gbé yín ní apá rẹ̀a ó bá yín ṣeré ní orúkún rẹ̀.

13. Gẹ́gẹ́ bí ìyá ti í tu ọmọ rẹ̀ nínú,bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò tù yín nínúa ó sì tù yín nínú lórí Jérúsálẹ́mù.”

14. Nígbà tí ẹ bá rí èyí, inú un yín yóò dùnẹ̀yin yóò sì gbilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí i koríko;ọwọ́ Olúwa ni a ó sọ di mímọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀,ṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ ni a ó fihàn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀.

15. Kíyèsí i, Olúwa ń bọ̀ pẹ̀lú ináàti kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ tí ó dàbí ìjì líle;òun yóò mú ìbínú rẹ ṣọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ìrunú,àti ìbáwí rẹ̀ pẹ̀lú ahọ́n iná.

16. Nítorí pẹ̀lú iná àti idàni Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ lóríi gbogbo ènìyàn,àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí Olúwa yóò pa.

Ka pipe ipin Àìsáyà 66