Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 45:14-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Ohun tí Olúwa wí nìyìí:“Àwọn èròjà ilẹ̀ Éjíbítì àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kúṣì,àti àwọn Ṣábíáṣì—wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹwọn yóò sì jẹ́ tìrẹ;wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn,wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́.Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀,wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé,‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì sí ẹlòmìíràn;kò sí ọlọ́run mìíràn.’ ”

15. Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́,Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Ísírẹ́lì

16. Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tìwọn yóò sì kan àbùkù;gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.

17. Ṣùgbọ́n Ísírẹ́lì ni a ó gbàlà láti ọwọ́ OlúwaPẹ̀lú ìgbàlà ayérayé;a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójú tì yín,títí ayé àìnípẹ̀kun.

18. Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí—ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run,Òun ni Ọlọ́run;ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé,Òun ló ṣe é;Òun kò dá a láti wà lófo,ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀—Òun wí pé:“Èmi ni Olúwa,kò sì sí ẹlòmìíràn.

19. Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó farasin,láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn;Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jákọ́bù pé‘Ẹ wá mi lórí asán.’Èmi Olúwa sọ òtítọ́;Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.

20. “Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá;ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìṣáǹṣá láti àwọnọrílẹ̀ èdè wá.Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri,tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.

21. Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wájẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀.Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́,ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe?Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa?Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi,Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà;kò sí ẹlòmìíràn àfi èmi.

22. “Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là,ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀-ayé;nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì sí ẹlòmìíràn.

23. Nípa èmi tìkálára mi ni mo ti búra,ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lúu gbogbo ipá miọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́:Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀;nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.

Ka pipe ipin Àìsáyà 45