Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àìsáyà 35:4-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Sọ fún àwọn oníbẹ̀rù ọkàn pé“Ẹ ṣe gírí, ẹ má bẹ̀rù;Ọlọ́run yín yóò wá,òun yóò wá pẹ̀lú ìgbẹ̀ṣan;pẹ̀lú ìgbẹ̀ṣan mímọ́òun yóò wá láti gbà yín là.”

5. Nígbà náà ni a ó la ojú àwọn afọ́júàti etí àwọn odi kì yóò dákẹ́.

6. Nígbà náà ni àwọn arọ yóò máa fò bí àgbọ̀nrín,àti ahọ́n odi yóò ké fún ayọ̀.Odò yóò tú jáde nínú ihààti àwọn odò nínú aṣálẹ̀.

7. Yanrìn tí ń jóná yóò di adágúnilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ yóò di orísun omi.Òpópó ibi tí àwọn ajáko sùn tẹ́lẹ̀ríkoríko àti koríko odò àti ewéko mìíràn yóò hù níbẹ̀.

8. Àti opópónà kan yóò wà níbẹ̀:a ó sì máa pè é ní ọ̀nà Ìwà-Mímọ́.Àwọn aláìmọ́ kì yóò tọ ọ̀nà náà;yóò sì wà fún àwọn tí ń rìn ní ọ̀nà náààwọn ìkà búburú kì yóò gba ibẹ̀ kọjá.

Ka pipe ipin Àìsáyà 35