Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 7:3-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Nísinsìn yìí àwọn ọkùnrin mẹ́rin kan wà pẹ̀lú ẹ̀tẹ̀ ní ẹnu àbáwọlé ibodè ìlú. Wọ́n wí fún olúkúlùkù pé, “kí ni ó dé tí àwa yóò fi jókòó síbí títí àwa yóò fi kú?

4. Tí àwa bá wí pé, ‘Àwa lọ sí ìlú, ìyàn wà níbẹ̀,’ àwa yóò sì kú. Tí àwa bá dúró níbí, a máa kú, ǹjẹ́ Nísinsìnyí ẹ jẹ́ kí a lọ sí ibùdó ti àwọn ará Síríà kí àwa kí ó sì tẹríba. Bí wọ́n bá dá wa sí, àwa yóò yè, tí wọ́n bá sì pa wá, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò kú.”

5. Ní àfẹ̀mójúmọ́ wọ́n dìde wọ́n sì lọ sí ibùdó àwọn ará Síríà. Nígbà tí wọ́n dé ẹ̀gbẹ́ ibùdó náà, kò sí ọkùnrin kan níbẹ̀,

6. Nítorí tí Olúwa jẹ́ kí àwọn ará Síríà gbọ́ ìró kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin àti ogun ńlá, wọ́n sì wí fún ara wọn pé, “Ẹ wò ó, ọba Ísírẹ́lì ti bẹ ogun àwọn Hítì àti àwọn ọba Ígíbítì láti dojúkọ mú u wá!”

7. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì dìde wọ́n sì sálọ ní àfẹ̀mọ́júmọ́ wọ́n sì fi àgọ́ wọn sílẹ̀ àti ẹṣin wọn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n sì fi ibùdó sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti wà, wọ́n sì sálọ fún ẹ̀mí wọn.

8. Nígbà tí àwọn ọkùnrin tí ó ní àrùn ẹ̀tẹ̀ dé ẹ̀gbẹ́ ibùdó wọ́n sì wọ inú ọ̀kan nínú àgọ́ náà. Wọ́n jẹ wọ́n sì mu, wọ́n sì kó fàdákà, wúrà àti ẹ̀wù, wọ́n sì lọ. Wọ́n sì wọ àgọ́ mìíràn lọ, wọ́n kó àwọn nǹkan láti ibẹ̀ wọ́n sì kó wọn pamọ́ pẹ̀lú.

9. Nígbà náà wọ́n wí fún ara wọn pé, “Àwa kò ṣe ohun rere. Oni yìí jẹ́ ọjọ́ ìròyìn rere àwa si paamọ́ ara wa. Tí àwa bá dúró títí di àfẹ̀mọ́júmọ́, ìjayà yóò jẹ́ ti wa. Ẹ jẹ́ kí a lọ ní ẹ̀ẹ̀kan kí a lọ ròyìn èyí fún àwọn ilé ọba.”

10. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì lọ wọ́n sì pe àwọn oníbodè wọ́n sì wí fún wọn pé, “Àwa lọ sí ibùdó àwọn ará Síríà kò sì sí ọkùnrin kankan níbẹ̀ tàbí ohùn ènìyàn kan àyàfi ẹṣin tí a so àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn àgọ́ náà sì wà gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti wà.”

11. Àwọn aṣọ́bodè náà pariwo ìròyìn náà, wọ́n sì sọ nínú ààfin.

12. Ọba sì dìde ní ùru ó sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Èmi yóò ṣọ fún yín ohun tí àwọn ará Ṣíríà tí ṣe fún wa. Wọ́n mọ̀ wí pé ebi ń pa wá; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ti kúrò ni ibùdó láti sá pamọ́ sí ẹ̀gbẹ́ ilé, wọ́n rò wí pé, ‘Wọn yóò jáde lóòtọ́, nígbà náà àwa yóò mú wọn ní ààyè àwa yóò yí wọ inú ìlú lọ.’ ”

13. Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ dáhùn pé, “Mú ọkùnrin díẹ̀ mú márùnún lára àwọn ẹsin tí wọ́n fi sílẹ̀ nínú ìlú. Ìwà wọn yóò dà bí gbogbo àwọn ará Ísírẹ́lì tí ó kù níbẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni, wọn yóò dà bí gbogbo àwọn Ísírẹ́lì, yìí nìkan tí a run. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ jẹ́ kí a rán wọn lọ láti lọ wo ohun tí ó ṣẹlẹ̀.”

14. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan kẹ̀kẹ́ méjì pẹ̀lú ẹsin wọn, ọba sì ránsẹ́ tọ ogun àwọn ará Síríà lẹ́yìn ó pàṣẹ fún àwọn awakọ̀ pé, “Ẹ lọ kí e lọ wo ohun tí ó ṣẹlẹ̀.”

15. Wọ́n sì tẹ̀lé wọn títí dé Jọ́dánì, wọ́n sì rí gbogbo ọ̀nà kún fún agbádá pẹ̀lú ohun èlò tí ará àwọn Ṣíríà gbé sọnù ní yàrá wọn. Ìránsẹ́ náà padà ó sì wá sọ fún ọba.

16. Nígbà náà àwọn ènìyàn jáde lọ ìkógun ní ibùdó àwọn ará Ṣíríà. Bẹ́ẹ̀ ni òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kan ni wọ́n tà fún Sẹ́kẹ́lì kan, àti òsùnwọ̀n báálì méjì ní Ṣékélì kan, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.

Ka pipe ipin 2 Ọba 7