Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Ọba 16:5-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Nígbà náà ni Résínì ọba Ṣíríà àti Pẹ́kà ọmọ Rèmálíà ọba Ísíráẹ́lì gòkè wá sí Jérúsálẹ́mù láti jagun: wọ́n dó ti Áhásì, ṣùgbọ́n wọn kò lè borí rẹ̀.

6. Ní àkókò náà, Résínì Ọba Ṣíríà gba Élátì padà fún Ṣíríà, ó sì lé àwọn ènìyàn Júdà kúrò ní Élátì: àwọn ará Ṣíríà sì wá sí Élíátì, wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ títí di òní yìí.

7. Áhásì sì rán oníṣẹ́ sọ́dọ̀ Tigilati-Pílésérì ọba Ásíríà wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni èmi, àti ọmọ rẹ; gòkè wá, kí o sì gbà mi lọ́wọ́ ọba Síríà, àti lọ́wọ́ ọba Ísírẹ́lì tí ó díde sí mi.”

8. Áhásì sì mú fàdákà àti wúrà tí a rí ní ilé Olúwa, àti nínú ìṣúrà ilé ọba, ó sì rán an sí ọba Ásíríà ní ọrẹ.

9. Ọba Ásíríà sì gbọ́ tirẹ̀: nítórí ọba Ásíríà gòkè wá sí Dámásíkù, ó sì kó o, ó sì mú un ní ìgbékùn lọ sí Kírì, ó sì pa Résínì.

10. Ọba sì lọ sí Dámásíkù láti pàdé Tigilati-Pílésérì, ọba Ásíríà, ó sì rí pẹpẹ kan tí ó wà ní Dámásíkù: Áhásì ọba sì rán àwòrán pẹpẹ náà, àti àpẹẹrẹ rẹ̀ sí Úráyà àlùfáà, gẹ́gẹ́ bí gbogbo iṣẹ́ ọ̀nà rẹ̀.

Ka pipe ipin 2 Ọba 16