Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 32:13-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. “Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ ohun tí èmi àti àwọn bàbá mi ti ṣe sí gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn? Ǹjẹ́ àwọn Ọlọ́run tí àwọn orílẹ̀ èdè mìíràn ní agbára láti gba ilẹ̀ wọn kúrò lọ́wọ́ mi?

14. Ta ni nínú gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀ èdè wọ̀nyí tí àwọn baba mi ti parun, tí ó le gbà ènìyàn rẹ̀ lọ́wọ́ mi, tí Ọlọ́run yín yóò fi le gbà yín lọ́wọ́ mi?

15. Nísinsinyìí, ẹ má ṣe jẹ́ kí Heṣekáyà ó tàn yín àti sì yín tọ́ sọ́nà báyìí. Ẹ má se gbàá gbọ́, nítorí tí kò sí Ọlọ́run orílẹ̀-èdè mìíràn tàbí ìjọba tí ó ní agbára láti gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi tàbí lọ́wọ́ àwọn bàbá mi, mélòómélòó wa ni Ọlọ́run yín tí yóò gbà yín kúrò lọ́wọ́ mi!”

16. Àwọn ìjòyè Senakéríbù sọ̀rọ̀ ṣíwájú síi ní ìlòdì sí Olúwa Ọlọ́run àti sí ìránṣẹ́ rẹ̀ Heṣekáyà.

17. Ọba pẹ̀lú sì kọ àwọn ìwé ní bíbú Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì àti ní sísọ èyí ní ìlòdì sí: “Ní gẹ́gẹ́ bí àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn ilẹ̀ mìíràn kò ṣe gba àwọn ènìyàn wọn kúrò lọ́wọ́ mi, Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run Heṣekáyà kì yóò gba àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi.”

18. Lẹ́yìn náà wọ́n pè jáde ní èdè Hébérù sí àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì tí ó wà lára ògiri, láti dá ọjọ́ si wọn, ki wọn kí ó lè fi agbára mú ìlú náà.

19. Wọ́n sọ̀rọ̀ nípa Ọlọ́run Jérúsálẹ́mù bí wọ́n ti ṣe nípa àwọn Ọlọ́run àwọn ènìyàn mìíràn ti àgbáyé, iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn.

20. Ọba Heṣekáyà àti wòlíì Àìṣáyà ọmọ Ámósì sunkún jáde nínú àdúrà sí ọ̀run nípa èyí.

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 32