Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kíróníkà 26:1-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà náà gbogbo ènìyàn Júdà mú Ùsáyà, ẹni tí ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínlógún (16) wọ́n sì fi jẹ ọba ní ipò baba rẹ̀ Ámásíà.

2. Òun ni ẹni náà tí ó tún Élótù kọ́, ó sì mú padà sí Júdà Lẹ́yìn ìgbà tí Ámásíà ti sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀.

3. Ùsáyà sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínlógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jérúsálẹ́mù fún ọdún méjìléláadọ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Jekolíà; ó sì wá láti Jérúsálẹ́mù.

4. Ó sì ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bi baba rẹ̀ Ámásíà ti ṣe.

5. Ó sì wá Olúwa ní ọjọ́ Sekaríà, ẹni tí ó ní òye nínú ìran Ọlọ́run. Níwọ̀n ọjọ́ tí ó wá ojú Olúwa, Ọlọ́run fún-un ní ohun rere.

6. Ó sì lọ sí ogun lórí Fílístínì ó sì wó odi Gátì lulẹ̀, Jábìnè àti Ásídódù. Ó sì kó ìlú rẹ̀ tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ Ásídódù àti níbì kan láàrin àwọn ará Fílístínì.

7. Ọlọ́run sì ràn án lọ́wọ́ lóri àwọn ará Fílístínì àti Árábù tí ń gbé ní Gúrì Bálì àti lórí àwọn ará Méhúmì.

8. Àwọn ará Ámórì gbé ẹ̀bùn wá fún Usíà, orúkọ rẹ̀ sì tàn káàkiri títí ó fi dé àtiwọ Éjíbítì, nítorí ó ti di alágbára ńlá.

9. Ùsáyà sì kọ́ ìlú sí Jérúsálẹ́mù níbi ẹnu bodè igun, àti nibi ẹnu bodè àfonífojì àti nibi ìṣẹ́po-odi ó sì mú wọn le

10. Ó sì tún ilé ìṣọ́ ihà kọ́, ó sì gbẹ́ kàǹga púpọ̀, nítorí ó ni ẹran ọ̀sìn púpọ̀ ní ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti ní pẹ̀tẹ́lẹ̀. Ó sì ní àwọn ènìyàn tí ń ṣiṣẹ́ ní pápá àti ọgbààjàrà ní orí òkè ní ilẹ̀ ọlọ́ràá, nítorí ó fẹ́ràn àgbẹ̀ ṣíṣe.

11. Úsíà sì ní àwọn ẹgbẹ́ ogun tí wọ́n kọ́ dáradára, wọ́n múra tán láti lọ pẹ̀lú ẹgbẹgbẹ́ gẹ́gẹ́ bí iye kíkà wọn gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ Jégíélì akọ̀wé àti Máséía ìjòyè lábẹ́ ọwọ́ Hánánì, ọ̀kan lára àwọn olórí ogun.

Ka pipe ipin 2 Kíróníkà 26