Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 20:35-42 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

35. Ó sì ṣe, ní òwúrọ̀ ni Jónátanì jáde lọ sí oko ní àkókò tí òun àti Dáfídì ti fí àdéhùn sí, ọmọdekùnrin kan sì wá pẹ̀lú rẹ̀.

36. Ó si wí fún ọmọdékùnrin rẹ̀ pé, “Sáré, kí o si wá àwọn ọfà tí èmi ó ta.” Bí ọmọdé náà sì ti ń sáré, òun sì tafà rékọjá rẹ̀.

37. Nígbà tí ọmọdékùnrin náà sì dé ibi ọfà tí Jónátanì ta, Jónátanì sì kọ sí ọmọdékùnrin náà ó sì wí pé, “Ọfà náà kò ha wà níwájú rẹ bi?”

38. Jónátanì sì kọ sí ọmọdékùnrin náà pé, “Sáré! Yára! Má ṣe dúró!” Ọmọdékùnrin Jónátanì sì ṣa àwọn ọfà náà, ó sì tọ olúwa rẹ̀ wá.

39. (Ọmọdékùnrin náà kò sì mọ̀ nǹkan; ṣùgbọ́n Jónátanì àti Dáfídì ni ó mọ ọ̀ràn náà.)

40. Jónátanì sì fí apó àti ọrun rẹ̀ fún ọmọdékùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Lọ, kí o sì mú wọn lọ sí ìlú Para.”

41. Bí ọmọdékùnrin náà ti lọ tán, Dáfídì sì dìde láti ibi òkúta náà, ó sì wólẹ̀, ó sì tẹríba ní ìdojúbolẹ̀ lẹ́ẹ̀mẹ́ta fún Jónátanì: wọ́n sì fi ẹnu ko ara wọn lẹ́nu, wọ́n sì jùmọ̀ sunkún, èkín-ín-ní pẹ̀lú ikejì rẹ̀, ṣùgbọ́n áfídì sunkún púpọ̀ jù.

42. Jónátanì sì wí fún Dáfídì pé, “Má a lọ ní àlàáfíà, bí o ti jẹ́ pé àwa méjèèjì tí júmọ búra ni orukọ Olúwa pé, ‘Ki Olúwa ó wà láàrin èmi àti ìwọ, láàrin irú-ọmọ mi àti láàrin irú-ọmọ rẹ̀ láéláé.’ ” Òun sì dìde, ó sì lọ kúrò: Jónátanì sì lọ sí ìlú.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 20