Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 20:34-42 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

34. Bẹ́ẹ̀ ni Jónátanì sì fi ìbínú dìde kúrò ni ibi oúnjẹ, kò sì jẹun ni ọjọ́ kejì oṣù náà, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ gidigidi fún Dáfídì, nítorí pé baba rẹ̀ dójú tì í.

35. Ó sì ṣe, ní òwúrọ̀ ni Jónátanì jáde lọ sí oko ní àkókò tí òun àti Dáfídì ti fí àdéhùn sí, ọmọdekùnrin kan sì wá pẹ̀lú rẹ̀.

36. Ó si wí fún ọmọdékùnrin rẹ̀ pé, “Sáré, kí o si wá àwọn ọfà tí èmi ó ta.” Bí ọmọdé náà sì ti ń sáré, òun sì tafà rékọjá rẹ̀.

37. Nígbà tí ọmọdékùnrin náà sì dé ibi ọfà tí Jónátanì ta, Jónátanì sì kọ sí ọmọdékùnrin náà ó sì wí pé, “Ọfà náà kò ha wà níwájú rẹ bi?”

38. Jónátanì sì kọ sí ọmọdékùnrin náà pé, “Sáré! Yára! Má ṣe dúró!” Ọmọdékùnrin Jónátanì sì ṣa àwọn ọfà náà, ó sì tọ olúwa rẹ̀ wá.

39. (Ọmọdékùnrin náà kò sì mọ̀ nǹkan; ṣùgbọ́n Jónátanì àti Dáfídì ni ó mọ ọ̀ràn náà.)

40. Jónátanì sì fí apó àti ọrun rẹ̀ fún ọmọdékùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Lọ, kí o sì mú wọn lọ sí ìlú Para.”

41. Bí ọmọdékùnrin náà ti lọ tán, Dáfídì sì dìde láti ibi òkúta náà, ó sì wólẹ̀, ó sì tẹríba ní ìdojúbolẹ̀ lẹ́ẹ̀mẹ́ta fún Jónátanì: wọ́n sì fi ẹnu ko ara wọn lẹ́nu, wọ́n sì jùmọ̀ sunkún, èkín-ín-ní pẹ̀lú ikejì rẹ̀, ṣùgbọ́n áfídì sunkún púpọ̀ jù.

42. Jónátanì sì wí fún Dáfídì pé, “Má a lọ ní àlàáfíà, bí o ti jẹ́ pé àwa méjèèjì tí júmọ búra ni orukọ Olúwa pé, ‘Ki Olúwa ó wà láàrin èmi àti ìwọ, láàrin irú-ọmọ mi àti láàrin irú-ọmọ rẹ̀ láéláé.’ ” Òun sì dìde, ó sì lọ kúrò: Jónátanì sì lọ sí ìlú.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 20