Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 22:33-43 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí i pé kì í ṣe ọba Ísírẹ́lì, wọ́n sì padà kúrò lẹ́yìn rẹ̀.

34. Ṣùgbọ́n ẹnìkan sì fa ọrun rẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, ó sì ta ọba Ísírẹ́lì láàrin ìpàdé ẹ̀wù irin. Ọba Ísírẹ́lì sì wí fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ dà, kí o sì mú mi jáde kúrò nínú ogun. Èmi ti gbọgbẹ́.”

35. Ogun náà sì le ní ọjọ́ náà, a sì dá ọba dúró nínú kẹ̀kẹ́ kọjú sí àwọn ará Árámù. Ẹ̀jẹ̀ sì sàn jáde láti inú ọgbẹ́ rẹ̀ sí àárin kẹ̀kẹ́ náà, ó sì kú ní àṣálẹ́.

36. A sì kéde la ibùdó já ní àkókò ìwọ̀ oòrùn wí pé, “Olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀ àti olúkúlùkù sí ilẹ̀ rẹ̀!”

37. Bẹ́ẹ̀ ni ọba kú, a sì gbé e wá sí Samáríà, wọ́n sì sin ín ní Samáríà.

38. Wọ́n sì wẹ kẹ̀kẹ́ náà ní adágún Samáríà, àwọn ajá sì lá ẹ̀jẹ̀ rè, àwọn àgbérè sì wẹ ara wọn nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti sọ.

39. Níti ìyókù ìṣe Áhábù, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ilé eyin-erin tí ó kọ́, àti gbogbo ìlú tí ó tẹ̀dó, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Ísírẹ́lì?

40. Áhábù sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Áhásáyà ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.

41. Jèhósáfátì ọmọ Áṣà, sì bẹ̀rẹ̀ sí ní jọba lórí Júdà ní ọdún kẹrin Áhábù ọba Ísírẹ́lì.

42. Jèhósáfátì sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ń jọba ní ọdún mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n ní Jérúsálẹ́mù. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Ásúbà ọmọbìnrin Sílíhì.

43. Ó sì rìn nínú gbogbo ọ̀nà Áṣà baba rẹ̀, kò sì yípadà kúrò nínú rẹ̀; ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa. Kìkì àwọn ibi gíga ni a kò mú kúrò, àwọn ènìyàn sì ń rú ẹbọ, wọ́n sì ń sun tùràrí níbẹ̀.

Ka pipe ipin 1 Ọba 22