12. Èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí ibí yìí àti àwọn tí ń gbé ní ibí yìí ni Olúwa wí. Èmi yóò mú ìlú yìí dàbí Tófẹ́tì.
13. Àwọn ilé tí ó wà ní Jérúsálẹ́mù àti ti Ọba ìlú Júdà ni a ó sọ di àìmọ́ gẹ́gẹ́ bí ti ibí yìí ní Tófẹ́tì gbogbo ilé tí wọ́n ti ń sun tùràrí ni orí àjà sí gbogbo ènìyàn tí ó sì ń da ọtí gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí Ọlọ́run mìíràn.’ ”
14. Jeremáyà sì padà láti Tófẹ́tì níbi tí Olúwa rán an sí láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ó sì dúró ní gbangba Tẹ́ḿpìlì Olúwa, ó sì sọ fún gbogbo ènìyàn pé,
15. “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ ogun, Ọlọ́run Ísíẹ́lì wí: ‘Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò mú ìdààmú tí mo ti sọ àṣọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ bá ìlú yìí àti ìgbéríko tí ó yí i ká, nítorí ọlọ́rùn líle ni wọ́n, wọn kò si ní fẹ́ fetí sí ọ̀rọ̀ mi.’ ”