Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1. Sam 12:6-15 Yorùbá Bibeli (YCE)

6. Samueli si wi fun awọn enia na pe, Oluwa li ẹniti o ti yan Mose ati Aaroni, on li ẹni ti o si mu awọn baba nyin goke ti ilẹ Egipti wá.

7. Njẹ nisisiyi ẹ duro jẹ, ki emi ki o le ba nyin sọ̀rọ niwaju Oluwa niti gbogbo iṣẹ ododo Oluwa, eyi ti on ti ṣe fun nyin ati fun awọn baba nyin.

8. Nigbati Jakobu wá si Egipti, ti awọn baba kigbe pe Oluwa, Oluwa si rán Mose ati Aaroni, awọn ẹniti o mu awọn baba nyin ti ilẹ Egypti jade wá, o si mu wọn joko nihinyi.

9. Nwọn si gbagbe Oluwa Ọlọrun wọn, o si tà wọn si ọwọ́ Sisera, olori ogun Hasori, ati si ọwọ́ awọn Filistini, ati si ọwọ́ ọba Moabu, nwọn si ba wọn jà.

10. Nwọn si kigbe pe Oluwa, nwọn si wipe, Awa ti dẹsẹ̀, nitoripe awa ti kọ̀ Oluwa silẹ, awa si ti nsin Baalimu ati Aṣtaroti: ṣugbọn nisisiyi, gba wa lọwọ́ awọn ọta wa, awa o si sìn ọ.

11. Oluwa si ran Jerubbaali, ati Bedani, ati Jefta ati Samueli, nwọn si gbà nyin lọwọ́ awọn ọta nyin niha gbogbo, ẹnyin si joko li alafia.

12. Nigbati ẹnyin si ri pe Nahaṣi ọba awọn ọmọ Ammoni tọ̀ nyin wá, ẹnyin wi fun mi pe, Bẹ̃kọ, ṣugbọn ọba yio jẹ lori wa: nigbati Oluwa Ọlọrun nyin jẹ ọba nyin.

13. Njẹ nisisiyi wo ọba na ti ẹnyin yàn, ati ti ẹnyin fẹ, kiye si i, Oluwa fi ọba jẹ fun nyin.

14. Bi ẹnyin ba bẹ̀ru Oluwa, ti ẹnyin si sin i, ti ẹnyin si gbọ́ ohùn rẹ̀, ti ẹnyin ko si tapa si ọ̀rọ Oluwa, ẹnyin ati ọba nyin ti o jẹ lori nyin yio ma wà lẹhin Oluwa Ọlọrun nyin.

15. Ṣugbọn bi ẹnyin ko ba gbà ohun Oluwa gbọ́, ti ẹ ba si tàpá si ọ̀rọ Oluwa, ọwọ́ Oluwa yio wà lara nyin si ibi, bi o ti wà lara baba nyin.

Ka pipe ipin 1. Sam 12