Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1. Kro 10:5-11 Yorùbá Bibeli (YCE)

5. Nigbati ẹniti o ru ihamọra rẹ̀ si ri pe Saulu kú, on na pẹlu si ṣubu le idà rẹ̀, o si kú.

6. Bẹ̃ni Saulu kú, ati awọn ọmọ rẹ̀ mẹtẹta, gbogbo ile rẹ̀ si kú ṣọkan.

7. Nigbati gbogbo awọn ọkunrin Israeli ti o wà ni pẹtẹlẹ ri pe nwọn sá, ati pe Saulu ati awọn ọmọ rẹ̀ kú, nwọn fi ilu wọn silẹ, nwọn si sá: awọn ara Filistia si wá; nwọn si joko ninu wọn.

8. O si ṣe ni ijọ keji, nigbati awọn ara Filistia de lati wá bọ́ awọn okú li aṣọ, nwọn si ri Saulu pẹlu, ati awọn ọmọ rẹ̀ pe; nwọn ṣubu li òke Gilboa.

9. Nwọn si bọ́ ọ li aṣọ, nwọn si gbé ori rẹ̀ ati ihamọra rẹ̀, nwọn si ranṣẹ si awọn ara Filistia yika, lati mu ihin lọ irò fun awọn ere wọn, ati fun awọn enia.

10. Nwọn si fi ihamọra rẹ̀ sinu ile oriṣa wọn, nwọn si kan agbari rẹ̀ mọ ile Dagoni.

11. Nigbati gbogbo Jabeṣ-gileadi gbọ́ gbogbo eyi ti awọn ara Filistia ti ṣe si Saulu,

Ka pipe ipin 1. Kro 10