Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nehemaya 5:1-11 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ọpọlọpọ àwọn eniyan náà, atọkunrin atobinrin, bẹ̀rẹ̀ sí tako àwọn Juu, arakunrin wọn.

2. Àwọn kan ń sọ pé, “Àwa, ati àwọn ọmọ wa, lọkunrin ati lobinrin, a pọ̀, ẹ jẹ́ kí á lọ wá ọkà, kí á lè máa rí nǹkan jẹ, kí á má baà kú.”

3. Àwọn mìíràn ń sọ pé, “A ti fi ilẹ̀ oko wa yáwó, ati ọgbà àjàrà wa, ati ilé wa, kí á lè rówó ra ọkà nítorí ìyàn tí ó mú yìí.”

4. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn mìíràn ń sọ pé, “A ti yá owó láti lè san owó ìṣákọ́lẹ̀ lórí ilẹ̀ oko ati ọgbà àjàrà wa.

5. Bẹ́ẹ̀ sì ni, bí àwọn arakunrin wa ti rí ni àwa náà rí, àwọn ọmọ wa kò yàtọ̀ sí tiwọn; sibẹsibẹ, à ń fi túlààsì mú àwọn ọmọ wa lọ sóko ẹrú, àwọn ọmọbinrin wa mìíràn sì ti di ẹrú pẹlu bẹ́ẹ̀ sì ni kò sí nǹkan tí a lè ṣe láti dáwọ́ rẹ̀ dúró, nítorí pé ní ìkáwọ́ ẹlòmíràn ni oko wa ati ọgbà àjàrà wa wà.”

6. Inú bí mi nígbà tí mo gbọ́ igbe wọn ati ohun tí wọn ń sọ.

7. Mo rò ó lọ́kàn mi, mo sì dá àwọn ọlọ́lá ati àwọn ìjòyè lẹ́bi. Mo sọ fún wọn pé, “Ẹ̀ ń ni àwọn arakunrin yín lára.”Mo bá pe ìpàdé ńlá lé wọn lórí, mo sọ fún wọn pé,

8. “Ní tiwa, a ti gbìyànjú níwọ̀n bí agbára wa ti mọ, a ti ra àwọn arakunrin wa tí wọ́n tà lẹ́rú fún àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn pada, ṣugbọn ẹ̀yin tún ń ta àwọn arakunrin yín, kí wọ́n baà lè tún tà wọ́n fún wa!” Wọ́n dákẹ́, wọn kò sì lè fọhùn.

9. Mo wá sọ pé, “Ohun tí ẹ̀ ń ṣe kò dára. Ǹjẹ́ kò yẹ kí ẹ máa fi ìbẹ̀rù rìn ní ọ̀nà Ọlọrun, kí àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ́ ọ̀tá wa má baà máa kẹ́gàn wa?

10. Pàápàá tí ó jẹ́ pé èmi ati àwọn arakunrin mi ati àwọn iranṣẹ mi ni à ń yá wọn ní owó ati oúnjẹ. Ẹ má gba èlé lọ́wọ́ wọn mọ́, ẹ sì jẹ́ kí á pa gbèsè wọn rẹ́.

11. Ẹ dá ilẹ̀ oko wọn pada fún wọn lónìí, ati ọgbà àjàrà wọn, ati ọgbà igi olifi wọn, ati ilé wọn, ati ìdá kan ninu ọgọrun-un owó èlé tí ẹ gbà, ati ọkà, waini, ati òróró tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn.”

Ka pipe ipin Nehemaya 5